Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ẹ̀dá ẹ̀mí tó sọ “ọ̀rọ̀ Jèhófà” tó wà ní 1 Àwọn Ọba 19:9 ló tún sọ̀rọ̀ ní “ohùn jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́, rírẹlẹ̀” yìí. Ní ẹsẹ 15, Bíbélì pe ẹ̀mí náà ní “Jèhófà.” Èyí lè rán wa létí ẹ̀dá ẹ̀mí kan tí Jèhófà rán níṣẹ́ láti máa tọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sọ́nà ní aginjù, tí Ọlọ́run sọ nípa rẹ̀ pé: “Orúkọ mi wà lára rẹ̀.” (Ẹ́kísódù 23:21) Òótọ́ ni pé, a kò lè sọ pàtó pé ẹni báyìí ni, àmọ́ Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé, ṣáájú kí Jésù tó wá sí ayé, ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí “Ọ̀rọ̀ náà,” ìyẹn Agbọ̀rọ̀sọ pàtàkì fún àwọn ìránṣẹ́ Jèhófà.—Jòhánù 1:1.