Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Tá a bá ń kọ́ èèyàn ní nǹkan, ó túmọ̀ sí pé à ń ran onítọ̀hún lọ́wọ́ láti “ronú kó sì máa hùwà lọ́nà tó yàtọ̀ sí bó ṣe ń ṣe tẹ́lẹ̀.” Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ ti ọdún 2020, ìyẹn Mátíù 28:19 jẹ́ ká rí bó ti ṣe pàtàkì tó pé ká máa kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, kí wọ́n ṣèrìbọmi, kí wọ́n sì dọmọ ẹ̀yìn Jésù Kristi. Torí náà, nínú àpilẹ̀kọ yìí àtèyí tó tẹ̀ lé e, a máa jíròrò àwọn nǹkan táá jẹ́ ká túbọ̀ já fáfá lẹ́nu iṣẹ́ tó ṣe pàtàkì jù yìí.