Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ìsíkíẹ́lì 37:1-14 àti Ìfihàn 11:7-12 tún sọ̀rọ̀ nípa ìmúbọ̀sípò tẹ̀mí tó ṣẹlẹ̀ lọ́dún 1919. Ìsíkíẹ́lì sọ tẹ́lẹ̀ nípa ìmúbọ̀sípò tẹ̀mí tó ṣẹlẹ̀ sí gbogbo àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró lẹ́yìn tí wọ́n ti pẹ́ ní ìgbèkùn. Àsọtẹ́lẹ̀ inú Ìfihàn sọ nípa àtúnbí tẹ̀mí tó ṣẹlẹ̀ sí díẹ̀ lára àwọn arákùnrin tó jẹ́ ẹni àmì òróró tí wọ́n ń ṣàbójútó nínú ètò Ọlọ́run. Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn táwọn ọ̀tá fi wọ́n sẹ́wọ̀n láìtọ́ fún àkókò díẹ̀, tí wọn ò sì lè ṣiṣẹ́ ìsìn Jèhófà. Lọ́dún 1919, Jèhófà sọ wọ́n di “ẹrú olóòótọ́ àti olóye.”—Mát. 24:45; wo ìwé Ìjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!, ojú ìwé 118.