Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Àwọn Ìwé Ìhìn Rere àtàwọn ìwé Bíbélì míì ṣàkọsílẹ̀ ìgbà ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ tí Jésù fara han àwọn èèyàn lẹ́yìn tó jíǹde. Bí àpẹẹrẹ, ó fara han Màríà Magidalénì (Jòh. 20:11-18); àwọn obìnrin míì (Mát. 28:8-10; Lúùkù 24:8-11); àwọn ọmọ ẹ̀yìn méjì (Lúùkù 24:13-15); Pétérù (Lúùkù 24:34); àwọn àpọ́sítélì, àmọ́ Tọ́másì ò sí níbẹ̀ (Jòh. 20:19-24); àwọn àpọ́sítélì pẹ̀lú Tọ́másì (Jòh. 20:26); méje lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ (Jòh. 21:1, 2); àwọn tó ju ọgọ́rùn-ún márùn-ún lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ (Mát. 28:16; 1 Kọ́r. 15:6); Jémíìsì àbúrò ẹ̀ (1 Kọ́r. 15:7); gbogbo àwọn àpọ́sítélì ẹ̀ (Ìṣe 1:4) àti àwọn àpọ́sítélì tó wà nítòsí Bẹ́tánì. (Lúùkù 24:50-52) Ó ṣeé ṣe kí Jésù tún fara han àwọn míì tí Bíbélì ò dárúkọ wọn.—Jòh. 21:25.