Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ẹ̀ṣẹ̀ tá a jogún látọ̀dọ̀ Ádámù, ọkùnrin àkọ́kọ́ ló mú kó máa wù wá láti ṣe ohun tí kò tọ́. Ádámù àti Éfà ìyàwó rẹ̀ dẹ́ṣẹ̀ sí Ọlọ́run, wọ́n pàdánù ìwàláàyè pípé tí wọ́n ní, àwọn ọmọ wọn náà sì di aláìpé.—Jẹ́nẹ́sísì 3:17-19; Róòmù 5:12.