Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ìwé Ìṣípayá fi ìsìn èké wé Bábílónì Ńlá, ìyẹn “aṣẹ́wó ńlá.” (Ìṣípayá 17:1, 5) Ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò tó máa pa Bábílónì Ńlá run ṣàpẹẹrẹ ètò kan tí wọ́n gbé kalẹ̀ láti so àwọn orílẹ̀-èdè ayé pọ̀, kó sì máa ṣojú wọn. Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-èdè ni àjọ tí wọ́n kọ́kọ́ gbé kalẹ̀ láti ṣe iṣẹ́ yìí, àmọ́ ní báyìí, ó ti di Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè.