Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Òótọ́ ni pé ìwé Gálátíà 5:19-21 mẹ́nu ba àwọn ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún (15) tó burú jáì, àmọ́ ìyẹn ò túmọ̀ sí pé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yẹn nìkan ló burú, torí lẹ́yìn tí Bíbélì mẹ́nu bà wọ́n, ó fi kún un pé “àti nǹkan báwọ̀nyí.” Torí náà, ó yẹ kí ẹni tó ń kà á fi òye mọ àwọn ohun tí Bíbélì ò tò sínú ẹsẹ yẹn, èyí tó pè ní “nǹkan báwọ̀nyí.”