Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Àwọn kan sọ pé ìtàn tó dá lórí bí áńgẹ́lì kan ṣe dá Pétérù sílẹ̀ lẹ́wọ̀n fi hàn pé Pétérù ní áńgẹ́lì kan tó ń dáàbò bò ó. (Ìṣe 12:6-16) Àmọ́ nígbà tí àwọn ọmọ ẹ̀yìn sọ pé “áńgẹ́lì [Pétérù]” ni, ó lè jẹ́ pé ṣe ni wọ́n rò pé áńgẹ́lì kan tó ń ṣojú fún Pétérù ló wá sọ́dọ̀ wọn, kì í ṣe Pétérù fúnra ẹ̀.