Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
e Bó tiẹ̀ jẹ́ pé inú ìwé Sekaráyà ni àsọtẹ́lẹ̀ yìí wà, síbẹ̀ Mátíù tó wà lára àwọn tó kọ Bíbélì sọ pé “nípasẹ̀ Jeremáyà wòlíì” la ṣe sọ ọ́. (Mátíù 27:9) Ó jọ pé nígbà míì, wọ́n máa ń fi ìwé Jeremáyà ṣáájú nínú apá tá a pè ní “Àwọn Wòlíì” nínú Ìwé Mímọ́. (Lúùkù 24:44) Ó jọ pé ṣe ni Mátíù pe àpapọ̀ àwọn ìwé kan, tó fi mọ́ ìwé Sekaráyà ní “Jeremáyà.”