Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Bíbélì pe Ọlọ́run ní Ẹni “tó ń gbé orí òbìrìkìtì ayé.” (Àìsáyà 40:22) Àwọn ìwé ìwádìí kan sọ pé ó ṣeé ṣe kí “òbìrìkìtì” tó wà nínú ẹsẹ Bíbélì yìí túmọ̀ sí ohun tó rí rogodo bíi bọ́ọ̀lù, àmọ́ kì í ṣe gbogbo àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n ló fara mọ́ èrò yìí. Síbẹ̀ náà, kò sí ẹ̀rí nínú Bíbélì tó fi hàn pé ayé rí pẹrẹsẹ.