Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Jèhófà la máa ń pe orúkọ Ọlọ́run lédè Yorúbà, ó jẹ́ ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ èdè Hébérù mẹ́rin yìí יהוה (YHWH), tó dúró fún orúkọ Ọlọ́run. Wọ́n túmọ̀ orúkọ yìí sí “Olúwa” nínú Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB). Tó o bá fẹ́ ìsọfúnni síwájú sí i nípa Jèhófà àti ìdí tí àwọn atúmọ̀ Bíbélì kan ò fi lo orúkọ yìí, wo àpilẹ̀kọ náà “Ta Ni Jèhófà?”