Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nínú àwọn Bíbélì kan, inú Sáàmù 22 làwọn ọ̀rọ̀ yìí wà. Àádọ́jọ [150] ni gbogbo Sáàmù tó wà lápapọ̀, àwọn Bíbélì kan tò ó bí wọ́n ṣe tò ó nínú ìwé Másórétì lédè Hébérù, nígbà tí àwọn Bíbélì míì tò ó bí wọ́n ṣe tò ó nínú Bíbélì Greek Septuagint, ìyẹn Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù tí wọ́n túmọ̀ sí èdè Gíríìkì, tí ìtumọ̀ rẹ̀ sì parí ní ọgọ́rùn-ún ọdún kejì Ṣáájú Sànmánì Kristẹni.