Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ọ̀mọ̀wé Jason David BeDuhn sọ pé bí ọ̀rọ̀ atọ́ka ò ṣe sí níwájú “Ọlọ́run” tó fara hàn lẹ́ẹ̀mejì nínú ẹsẹ Bíbélì yẹn jẹ́ ká rí i pé ìyàtọ̀ wà láàárín àwọn méjèèjì, bí a ṣe máa ń fi ìyàtọ̀ sáàárín ‘ọlọ́run kan’ àti ‘Ọlọ́run’ tá a bá ń kọ̀wé lédè Yorùbá.” Ó fi kún un pé: “Ní Jòhánù 1:1, Ọ̀rọ̀ náà kì í ṣe Ọlọ́run Olódùmarè kan ṣoṣo náà, àmọ́ ó jẹ́ ọlọ́run kan tàbí ẹ̀dá alágbára.”—Truth in Translation: Accuracy and Bias in English Translations of the New Testament, ojú ìwé 115, 122 àti 123.