ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2026)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Wednesday, October 15

Èmi ni Ááfà àti Ómégà.—Ìfi. 1:8.

Ááfà ni lẹ́tà àkọ́kọ́ nínú álífábẹ́ẹ̀tì èdè Gíríìkì, ómégà sì ni lẹ́tà tó kẹ́yìn. Torí náà, nígbà tí Jèhófà sọ pé òun ni “Ááfà àti Ómégà,” ohun tó ń sọ ni pé tóun bá bẹ̀rẹ̀ nǹkan, ó dájú pé òun máa parí ẹ̀. Lẹ́yìn tí Jèhófà dá Ádámù àti Éfà, ó sọ fún wọn pé: “Ẹ máa bímọ, kí ẹ sì pọ̀, kí ẹ kún ayé, kí ẹ sì ṣèkáwọ́ rẹ̀.” (Jẹ́n. 1:28) Ìgbà tí Jèhófà sọ̀rọ̀ yìí ni “Ááfà.” Àmọ́ lọ́jọ́ iwájú, nígbà táwọn àtọmọdọ́mọ Ádámù àti Éfà tí wọ́n jẹ́ onígbọràn bá kún ayé, tí wọ́n sì sọ ọ́ di Párádísè ni Jèhófà máa sọ pé “Ómégà.” Lẹ́yìn tí Ọlọ́run dá “ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tó wà nínú wọn” tán, ó sọ ohun tó fi hàn pé òun máa mú ìlérí òun ṣẹ. Ó sọ pé òun máa ṣe ohun tóun ní lọ́kàn fáwa èèyàn àti ayé ní òpin ọjọ́ keje.—Jẹ́n. 2:​1-3. w23.11 5 ¶13-14

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Thursday, October 16

Ẹ tún ọ̀nà Jèhófà ṣe! Ẹ la ọ̀nà tó tọ́ gba inú aṣálẹ̀ fún Ọlọ́run wa.—Àìsá. 40:3.

Ó máa gba nǹkan bí oṣù mẹ́rin káwọn ọmọ Ísírẹ́lì tó lè rìnrìn àjò láti Bábílónì pa dà sí Ísírẹ́lì, àmọ́ Jèhófà ṣèlérí pé ohunkóhun tó máa dí wọn lọ́wọ́ tí ò ní jẹ́ kí wọ́n pa dà lòun máa mú kúrò lọ́nà. Àwọn Júù olóòótọ́ yẹn mọ̀ pé àǹfààní táwọn máa rí táwọn bá pa dà sí Ísírẹ́lì ju ohunkóhun táwọn máa fi sílẹ̀ ní Bábílónì lọ. Àǹfààní tó ga jù tí wọ́n máa rí ni pé wọ́n á máa jọ́sìn Jèhófà. Kò sí tẹ́ńpìlì Jèhófà kankan ní Bábílónì. Òfin Mósè sì sọ pé káwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa rúbọ, àmọ́ kò sí pẹpẹ kankan tí wọ́n ti lè rúbọ sí Jèhófà níbẹ̀, kò tún sí àwọn àlùfáà tí wọ́n á máa rú àwọn ẹbọ náà. Yàtọ̀ síyẹn, àwọn abọ̀rìṣà tí ò bọ̀wọ̀ fún Jèhófà àtàwọn ìlànà ẹ̀ pọ̀ ju àwọn èèyàn Jèhófà lọ. Torí náà, ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn Júù tó bẹ̀rù Ọlọ́run ń retí ìgbà tí wọ́n máa pa dà sí ìlú ìbílẹ̀ wọn, kí wọ́n lè pa dà bẹ̀rẹ̀ ìjọsìn mímọ́. w23.05 14-15 ¶3-4

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Friday, October 17

Ẹ máa rìn gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìmọ́lẹ̀.—Éfé. 5:8.

Ó ṣe pàtàkì pé kí ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run ràn wá lọ́wọ́ tá a bá fẹ́ jẹ́ “ọmọ ìmọ́lẹ̀.” Kí nìdí? Ìdí ni pé kò rọrùn láti jẹ́ oníwà mímọ́ nínú ayé tó kún fún ìṣekúṣe yìí. (1 Tẹs. 4:​3-5, 7, 8) Ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run lè ràn wá lọ́wọ́ láti borí èrò burúkú tí ayé ń gbé lárugẹ, títí kan àwọn ọgbọ́n orí èèyàn àtàwọn èrò tí ò bá ìlànà Ọlọ́run mu. Yàtọ̀ síyẹn, ẹ̀mí mímọ́ tún máa jẹ́ ká ní “oríṣiríṣi ohun rere àti òdodo.” (Éfé. 5:9) Báwo la ṣe lè rí ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run gbà? Ọ̀nà kan tá a lè gbà ṣe bẹ́ẹ̀ ni pé ká máa gbàdúrà pé kí Jèhófà fún wa. Jésù sọ pé Jèhófà “máa fi ẹ̀mí mímọ́ fún àwọn tó ń béèrè lọ́wọ́ rẹ̀.” (Lúùkù 11:13) Yàtọ̀ síyẹn, a tún máa ń rí ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run gbà tá a bá ń yin Jèhófà pẹ̀lú àwọn ará nípàdé. (Éfé. 5:​19, 20) Torí náà, ẹ̀mí mímọ́ máa jẹ́ ká láwọn ìwà táá jẹ́ ká máa múnú Ọlọ́run dùn. w24.03 23-24 ¶13-15

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́