-
“Bóyá Ó Máa Yí Padà Lọ́tẹ̀ Yìí”Jí!—2001 | November 8
-
-
“Bóyá Ó Máa Yí Padà Lọ́tẹ̀ Yìí”
ARA Roxanaa yá mọ́ èèyàn, arẹwà obìnrin ni, ó sì lọ́mọ mẹ́rin, oníṣègùn iṣẹ́ abẹ tó gbayì gan-an lọkọ rẹ̀ ní Gúúsù Amẹ́ríkà. Obìnrin yìí sọ pé: “Àwọn obìnrin fẹ́ràn ọkọ mi gan-an, àwọn ọkùnrin pẹ̀lú sì gba tiẹ̀.” Àmọ́ ohun kan ba ọkọ Roxana jẹ́, ohun táwọn ọ̀rẹ́ wọn tímọ́tímọ́ pàápàá kò mọ̀. “Kìnnìún ni lọ́dẹ̀dẹ̀. Òjòwú pọ́ńbélé sì ni.”
Àìbalẹ̀ ọkàn hàn lójú Roxana bó ṣe ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ. “Kò ju ọ̀sẹ̀ bíi mélòó kan lọ tá a ṣègbéyàwó ni ìṣòro náà bẹ̀rẹ̀. Àwọn àbúrò mi ọkùnrin àti ìyá mi wá kí wa, a jọ ṣeré tá a sì gbádùn ara wa dáadáa. Àmọ́ nígbà tí wọ́n lọ tán, tìbínú-tìbínú lọkọ mi fi jù mí lu àga ìjókòó, ìbínú ti ru bò ó lójú. Bí àlá lọ̀rọ̀ ọ̀hún ṣe rí lójú mi.”
Ó mà ṣe o, bí wàhálà Roxana ṣe bẹ̀rẹ̀ wẹ́rẹ́ nìyẹn o, fún ọ̀pọ̀ ọdún lọkọ rẹ̀ ti lù ú léraléra nílù bàrà. Ńṣe ni Roxana máa ń jìyà ní àjẹ-ǹjẹ-tún-jẹ. Ọkọ rẹ̀ á nà án, lẹ́yìn náà láá wá bẹ̀ ẹ́ gan-an pé òun ò tún ní ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́ láé. Ó máa ń tọwọ́ ọmọ rẹ̀ baṣọ fún ìgbà díẹ̀. Àmọ́ bó bá ṣe sàà, wàhálà ọ̀hún á tún bẹ̀rẹ̀. Roxana sọ pé: “Ohun tí mo máa ń rò ni pé bóyá ó máa yí padà lọ́tẹ̀ yìí. Kódà bí mo bá sá kúrò nílé pàápàá, màá tún padà lọ bá a.”
Ohun tó máa ń já Roxana láyà ni pé ọjọ́ kan á jọ́kan tí ìwà ipá ọkọ rẹ̀ yìí á tún burú jù bẹ́ẹ̀ lọ. Ó sọ pé: “Ó ti sọ ọ́ rí pé òun á pa èmi àtàwọn ọmọ, àtòun fúnra rẹ̀. Ó ti gbé sáàsì sí mi lọ́fun rí. Ó tiẹ̀ ti fẹ́ fìbọn pa mí rí, ó gbé e sí etí mi, ó sì yin ìbọn náà! Ọlá pé kò sí ọta nínú rẹ̀ ni mo jẹ, àmọ́ jìnnìjìnnì ọ̀hún fẹ́rẹ̀ẹ́ pa mí.”
Mẹ́nu Mọ́ Làwọn Obìnrin Ń Fi Ọ̀rọ̀ Náà Ṣe
Bíi ti Roxana, àràádọ́ta ọ̀kẹ́ àwọn obìnrin kárí ayé ní ń jẹ dẹndẹ ìyà lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin tí kò láàánú lójú.b Ọ̀pọ̀ wọn kò jẹ́ sọ iná tó ń jó wọn lábẹ́ aṣọ síta. Èrò wọn ni pé bí wọ́n bá fẹjọ́ sun àwọn tí ọkọ wọn bẹ̀rù, kò sóhun tó máa tìdí ẹ̀ yọ. Ó ṣe tán, ọ̀pọ̀ àwọn aṣeniléṣe ọkọ bẹ́ẹ̀ ló ti sọ pé irọ́ ni ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn wọ́n, bíi kí wọ́n sọ pé, “Nǹkan ti tètè máa ń bí ìyàwó mi nínú jù,” tàbí “Ó ti máa ń fi kún ọ̀rọ̀ ju bó ṣe yẹ lọ.”
Ọ̀ràn ìbànújẹ́ ló jẹ́ pé ọ̀pọ̀ obìnrin lọkàn wọn máa ń kó sókè lójoojúmọ́ nítorí ìbẹ̀rù ìgbájú-ìgbámú nínú ilé tó ti yẹ kí ọkàn wọn balẹ̀ jù lọ. Síbẹ̀, ẹni tó ń fìyà jẹ èèyàn ni wọ́n sábàá máa ń fojú àánú hàn sí lọ́pọ̀ ìgbà dípò ẹni tá a ń fìyà jẹ. Kódà, àwọn kan ò tiẹ̀ lè gbà pé ọkùnrin kan táwọn èèyàn ń ṣe sàdáńkátà fún lè máa na ìyàwó rẹ̀. Gbé ohun tó ṣẹlẹ̀ sí obìnrin kan tó ń jẹ́ Anita yẹ̀ wò nígbà tó ké gbàjarè lórí bí ọkọ rẹ̀ táwọn èèyàn ń bọ̀wọ̀ fún ṣe ń lù ú. “Ọ̀kan lára àwọn ojúlùmọ̀ wa sọ fún mi pé: ‘Kí ló mú ẹ fẹ̀sùn kan ọ̀gbẹ́ni táwọn èèyàn ń wárí fún yìí?’ Òmíràn sọ pé ó ní láti jẹ́ pé èmi ni mò ń fín in níràn! Kódà nígbà tí àṣírí ọkọ mi tiẹ̀ wá tú pàápàá, ńṣe làwọn ọ̀rẹ́ mi kan bẹ̀rẹ̀ sí yàn mí lódì. Wọn rò pé ó yẹ kí n máa mú un mọ́ra nítorí pé ‘bẹ́ẹ̀ làwọn ọkùnrin ṣe rí.’”
Gẹ́gẹ́ bá a ṣe rí i nínú ìrírí Anita, ó ṣì ṣòro fún ọ̀pọ̀ láti gbà pé àwọn ọkùnrin kan ń han ìyàwó wọn léèmọ̀. Kí ló lè mú kí ọkùnrin kan máa hùwà òǹrorò sí obìnrin tó sọ pé òun nífẹ̀ẹ́? Báwo la ṣe lè ran àwọn tí ìyà ń jẹ yìí lọ́wọ́?
-
-
Kí Ló Dé Táwọn Ọkùnrin Kan Fi Máa Ń Lu Ìyàwó Wọn?Jí!—2001 | November 8
-
-
Kí Ló Dé Táwọn Ọkùnrin Kan Fi Máa Ń Lu Ìyàwó Wọn?
ÀWỌN ògbógi kan sọ pé ó ṣeé ṣe kí iye àwọn obìnrin táwọn ọkọ wọn ń pa ju iye àwọn obìnrin tó ń kú nípasẹ̀ gbogbo nǹkan tó ń ṣekú pa obìnrin láyé yìí. Onírúurú ìwádìí làwọn èèyàn ti ṣe nítorí àtifòpin sí ìwà kí ọkùnrin máa lu ìyàwó rẹ̀. Irú ọkùnrin wo ló tiẹ̀ máa ń lu ìyàwó rẹ̀? Báwo ni wọ́n ṣe tọ́ ọ dàgbà? Ṣé kìígbọ́-kìígbà ni nígbà tí wọ́n ń fẹ́ra sọ́nà? Tí àwọn dókítà afìṣemọ̀rònú bá ń bá ẹni tó ń lu ìyàwó rẹ̀ yìí sọ̀rọ̀ nípa ìwà ipá náà, ṣé ó máa ń tẹ́wọ́ gba ìmọ̀ràn náà?
Ohun kan táwọn ògbógi ti kíyè sí ni pé àwọn ọkọ tó ń lu ìyàwó wọn kò rí bákan náà. Àwọn kan wà tó jẹ́ pé ẹ̀ẹ̀kọ̀ọ̀kan ni wọ́n máa ń hùwà ipá yìí. Irú ẹni bẹ́ẹ̀ kì í lo àwọn ohun ìjà kò sì sí lákọọ́lẹ̀ rẹ̀ pé ó ń lu ìyàwó rẹ̀ léraléra. Kì í ṣe àṣà irú ẹni yìí láti máa hùwà ipá àmọ́ ipò àyíká àti àwùjọ tó wà ló mú kó máa ṣe bẹ́ẹ̀. Ibẹ̀ sì ni ọkùnrin mìíràn wà tó jẹ́ pé lílu ìyàwó rẹ̀ ní àlùpa-mókùú ti di mọ́ọ́lí sí i lára. Gbogbo ìgbà ló máa ń hùwà yìí, kò sì jẹ́ ronú rárá pé nǹkan tóun ń ṣe kù díẹ̀ káàtó.
Àmọ́ ṣá, pé oríṣiríṣi làwọn ọkùnrin tó ń lu ìyàwó wọn yìí kò túmọ̀ sí pé àwọn ọ̀nà kan wà tí wọ́n ń gbà ṣe é tí kò burú o. Ká sòótọ́, líluni lọ́nà èyíkéyìí lè fa ọgbẹ́, kódà ó lè fa ikú pàápàá. Nítorí náà, ti pé ọkùnrin kan kì í hùwà jàgídíjàgan yìí ní gbogbo ìgbà tàbí pé tiẹ̀ kò burú tó ti ẹlòmíràn kò fi hàn pé ìwà náà dára. Ní ti gidi, kò sóhun tó ń jẹ́ líluni “lọ́nà tó dára.” Nígbà náà, kí ló lè wá mú kí ọkùnrin kan máa lu obìnrin tó jẹ́jẹ̀ẹ́ pé òun á ṣìkẹ́ títí ọjọ́ ayé òun?
Ipa Tí Ìdílé Tí Wọ́n Ti Wá Ń Kó
Kò yani lẹ́nu pé inú ìdílé oníjàgídíjàgan ni wọ́n ti tọ́ lára àwọn ọkùnrin tó máa ń lu ìyàwó wọn yìí dàgbà. Michael Groetsch, tó ti fi ohun tó lé ní ogún ọdún ṣèwádìí nípa báwọn ọkùnrin ṣe ń han ìyàwó wọn léèmọ̀ kọ̀wé pé: “Inú ìdílé tó dà bí ‘ojú ogun’ ni wọ́n ti tọ́ ọ̀pọ̀ àwọn ọkùnrin tó ń lu ìyàwó wọn dàgbà. Àyíká burúkú tí kò ti sóhun tó ‘burú’ nínú kéèyàn gbèrò ibi tàbí hùwà ibi ni wọ́n ti ṣe èwe, ibẹ̀ ni wọ́n sì ti dàgbà.” Ògbóǹtagí kan sọ pé, ọkùnrin tí wọ́n bá tọ́ dàgbà nírú àyíká bẹ́ẹ̀ “lè ti kékeré bẹ̀rẹ̀ sí ní irú ìkórìíra tí bàbá rẹ̀ ní fún àwọn obìnrin. Ohun tí ọmọ yẹn á kọ́ ni pé ọkùnrin ló gbọ́dọ̀ máa darí àwọn obìnrin, àti pé ọ̀nà tí ipò orí yẹn fi lè dọ́wọ́ rẹ̀ ni pé kó máa dẹ́rù bà wọ́n, kó máa hàn wọ́n léèmọ̀, kó sì máa yẹ̀yẹ́ wọn. Lọ́wọ́ kan náà, á tún kọ́ pé ọ̀nà kan ṣoṣo tí inú bàbá òun fi lè dùn sí òun ni kóun máa hùwà bó ṣe ń hùwà.”
Bíbélì sọ ọ́ ní kedere pé ìwà òbí lè ní ipa lórí ọmọ gan-an, yálà ipa tó dára tàbí èyí tí kò dára. (Òwe 22:6; Kólósè 3:21) Lóòótọ́, bí wọ́n ṣe tọ́ èèyàn dàgbà kò torí ẹ̀ sọ pé kéèyàn máa lu ìyàwó rẹ̀, àmọ́ ó lè ṣèrànwọ́ láti jẹ́ ká lóye ibi tí ìwà ipá yìí ti ṣẹ̀ wá.
Àṣà Ìbílẹ̀ Ní Ipa Tó Ń Kó
Ní àwọn ilẹ̀ kan kò sóhun tó burú nínú kéèyàn na obìnrin, déédéé ló ṣe. Ìròyìn kan látọ̀dọ̀ Àjọ Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè sọ pé: “Láwọn àgbègbè tó pọ̀, ọwọ́ dan-in dan-in ni wọ́n fi ń mú ẹ̀tọ́ tí ọkọ ní láti lu ìyàwó rẹ̀ tàbí kó fayé sú u.”
Àní láwọn ilẹ̀ tí wọn ò ti fara mọ́ irú ìwàkiwà bẹ́ẹ̀, ọ̀pọ̀ làwọn tó ti bẹ̀rẹ̀ sí ṣe bẹ́ẹ̀ láyè ara wọn. Èrò àwọn ọkùnrin kan nípa ọ̀ràn yìí bani lẹ́rù. Gẹ́gẹ́ bí ìwé ìròyìn Weekly Mail and Guardian ti Gúúsù Áfíríkà ti sọ, ìwádìí kan tí wọ́n ṣe níbi Ìyawọlẹ̀ Omi Cape fi hàn pé ọ̀pọ̀ àwọn ọkùnrin tó sọ pé àwọn kì í lu ìyàwó àwọn sọ pé kò sóhun tó burú nínú kéèyàn gbá ìyàwó rẹ̀ lẹ́ṣẹ̀ẹ́, ìyẹn kò sì túmọ̀ sí ìwà ipá.
Ní tòótọ́, àtìgbà ọmọdé lèrò tó lòdì bẹ́ẹ̀ ti ń bẹ̀rẹ̀. Fún àpẹẹrẹ, ní ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì, ìwádìí kan fi hàn pé ìdá márùndínlọ́gọ́rin nínú ọgọ́rùn-ún àwọn ọmọkùnrin ọlọ́dún mọ́kànlá sí méjìlá ló sọ pé bí inú bá ń bí ọkùnrin, ó lè kó ẹ̀ṣẹ́ bo obìnrin.
Ohun Tí Ò Dáa Kò Dáa
Àwọn ohun tá a sọ lókè yìí lè jẹ́ ká lóye nǹkan tó ń mú káwọn ọkùnrin kan máa lu ìyàwó wọn, àmọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyẹn ò sọ pé ó dára láti lu ìyàwó ẹni. Ká kúkú sọ ojú abẹ níkòó, ẹ̀ṣẹ̀ ńlá gbáà ni lílu ìyàwó ẹni jẹ́ lójú Ọlọ́run. A kà á nínú Bíbélì tó jẹ́ Ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé: “Ó yẹ kí àwọn ọkọ máa nífẹ̀ẹ́ àwọn aya wọn gẹ́gẹ́ bí ara àwọn fúnra wọn. Ẹni tí ó bá nífẹ̀ẹ́ aya rẹ̀ nífẹ̀ẹ́ ara rẹ̀, nítorí pé kò sí ènìyàn kankan tí ó jẹ́ kórìíra ara òun fúnra rẹ̀; ṣùgbọ́n a máa bọ́ ọ, a sì máa ṣìkẹ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Kristi pẹ̀lú ti ń ṣe sí ìjọ.”—Éfésù 5:28, 29.
Ó ti pẹ́ tí Bíbélì ti sọ ọ́ pé ní “àwọn ọjọ́ ìkẹyìn” ètò àwọn nǹkan yìí, ọ̀pọ̀ èèyàn ló máa di “afìyàjẹni, aláìnífẹ̀ẹ́, àti òǹrorò.” (2 Tímótì 3:1-3; The New English Bible) Bí àṣà kí ọkùnrin máa lu ìyàwó rẹ̀ ṣe ń gbèèràn káàkiri yìí jẹ́ ohun mìíràn tó fi hàn pé àkókò tí àsọtẹ́lẹ̀ yìí sọ gan-an la wà yìí. Àmọ́ kí la lè ṣe láti ran àwọn tó ń jẹ irú ìyà yìí lọ́wọ́? Ǹjẹ́ ìrètí wà pé àwọn ọkùnrin tó ń lu ìyàwó wọn lè yí padà?
[Ìsọfúnni tá a pàfiyèsí sí ní ojú ìwé 5]
“Ẹnì kan tó lu ìyàwó rẹ̀ kò yàtọ̀ sí ọkùnrin arúfin kan tó da ẹ̀ṣẹ́ bo ẹni tí kò mọ̀ rí.”—When Men Batter Women
[Àpótí tó wà ní ojú ìwé 6]
Kí Ọkọ Máa Lu Aya Ó Ti Di Ìṣòro Kárí Ayé
Lílù tí àwọn ọkùnrin onígbèéraga ń lu àwọn ìyàwó wọn ti di ìṣòro tó kárí ayé o, àwọn ìròyìn tó wà nísàlẹ̀ yìí fi èyí hàn.
Íjíbítì: Ìwádìí olóṣù mẹ́ta tí wọ́n ṣe ní Alẹkisáńdíríà fi hàn pé ìwà ipá nínú ilé lohun tó ń dá ọgbẹ́ sára àwọn obìnrin jù lọ. Òun ló ń mú ohun tó fẹ́rẹ̀ẹ́ tó ìdá ọgbọ̀n nínú ọgọ́rùn-ún gbogbo àwọn obìnrin lọ sí ilé ìtọ́jú ọgbẹ́.—Résumé 5 of the Fourth World Conference on Women.
Thailand: Ní àgbègbè tó tóbi jù lọ ní ìlú Bangkok, ìdá àádọ́ta nínú ọgọ́rùn-ún àwọn obìnrin tó wà nílé ọkọ lọkọ wọn máa ń lù déédéé.—Pacific Institute for Women’s Health.
Hong Kong: “Iye àwọn obìnrin tó sọ pé ọkọ wọn ti lù wọ́n rí ti fi iye tó lé ní ìpín ogójì nínú ọgọ́rùn-ún lọ sókè lẹ́nu ọdún tó kọjá.”—South China Morning Post, July 21, 2000.
Japan: Iye àwọn obìnrin tó ń wá ibi tí wọ́n máa sá lọ ti lọ sókè látorí nǹkan bí ẹgbẹ̀rún márùn-ún lọ́dún 1995 sí ohun tó fẹ́rẹ̀ẹ́ tó ẹgbẹ̀rún mẹ́fà àtààbọ̀ lọ́dún 1998. “Nǹkan bí ìdá kan nínú mẹ́ta wọn sọ pé ìwà ipá ọkọ wọn ló jẹ́ káwọn máa wá ibi táwọn máa sá lọ.”—The Japan Times, September 10, 2000.
Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì: “Láàárín ìṣẹ́jú àáyá mẹ́fà péré, wọ́n á fipá ba ẹnì kan lòpọ̀, wọ́n á lu ẹnì kan tàbí gún un lọ́bẹ nínú ilé kan nílẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì.” Gẹ́gẹ́ bí ìròyìn kan látọ̀dọ̀ àwọn ọlọ́pàá ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì ṣe sọ, “àwọn ọlọ́pàá ń gba ìpè ọgọ́rùn-ún dín légbèje [1,300] lójoojúmọ́ látọ̀dọ̀ àwọn tá a ń fìyà jẹ nínú ilé, iye ìpè bẹ́ẹ̀ sì ju ọ̀kẹ́ méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé ẹgbàárùn-ún [570,000] lọ lọ́dún. Ìdá mọ́kànlélọ́gọ́rin nínú ọgọ́rùn-ún ló jẹ́ àwọn obìnrin táwọn ọkùnrin ń hàn léèmọ̀.”—The Times, October 25, 2000.
Peru: Ìpín àádọ́rin nínú ọgọ́rùn-ún ìwà ipá tá a fi tó àwọn ọlọ́pàá létí ló jẹ́ ti àwọn obìnrin táwọn ọkọ wọn lù.—Pacific Institute for Women’s Health.
Rọ́ṣíà: “Ní ọdún kan péré, ẹgbẹ̀rún mẹ́rìnlá àtààbọ̀ [14,500] làwọn obìnrin ará Rọ́ṣíà táwọn ọkọ wọn ń pa, tí àwọn ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé irínwó [56,400] sì ń di amúkùn-ún tàbí kí wọ́n gbọgbẹ́ yánna-yànna nípasẹ̀ ìwà ipá inú ilé.”—The Guardian.
China: Ọ̀jọ̀gbọ́n Chen Yiyun, tó jẹ́ olùdarí Ibùdó Ọ̀ràn Ìdílé ti ìlú Jinglun, sọ pé: “Kò tíì pẹ́ tí ìṣòro yìí bẹ̀rẹ̀. Ó sì ti ń gbilẹ̀ gan-an, àgàgà láwọn ìgboro. Gbogbo bí àwọn kan ṣe lòdì sí i kò ní kó dáwọ́ dúró.”—The Guardian.
Nicaragua: “Ńṣe ni híhùwà ipá sáwọn obìnrin ní Nicaragua ń peléke sí i. Ìwádìí kan fi hàn pé lọ́dún tó kọjá nìkan, ìdá méjìléláàádọ́ta àwọn obìnrin Nicaragua ló ń jìyà nípasẹ̀ oríṣi ìwà ipá inú ilé kan tàbí òmíràn látọ̀dọ̀ àwọn ọkọ wọn.”—Ìròyìn orí rédíò BBC.
[Àpótí tó wà ní ojú ìwé 7]
Àwọn Àmì Tó Ń Fi Hàn Pé Ewu Ń Bẹ
Gẹ́gẹ́ bí ìwádìí tí Richard J. Gelles ṣonígbọ̀wọ́ rẹ̀ ní Yunifásítì Rhode Island, ní Orílẹ̀-Èdè Amẹ́ríkà ṣe sọ, àwọn ohun tó wà nísàlẹ̀ yìí ni àwọn nǹkan tó máa ń fa kí ọkọ máa lu ìyàwó rẹ̀ tàbí kó máa sọ̀rọ̀ kòbákùngbé sí i nínú ilé:
1. Ọkùnrin náà ti lọ́wọ́ nínú ìwà ipá inú ilé nígbà kan rí.
2. Ọkùnrin náà kò níṣẹ́ lọ́wọ́.
3. Ó máa ń lo oògùn olóró ní ó kéré tán ẹ̀ẹ̀kan lọ́dún.
4. Nígbà tó ṣì wà lọ́dọ̀ àwọn òbí rẹ̀, ó máa ń rí i bí bàbá rẹ̀ ṣe máa ń lu ìyá rẹ̀.
5. Ọkùnrin àti obìnrin náà kò fẹ́ra wọn níṣu-lọ́kà; wọ́n kàn jọ ń gbé ni.
6. Tí ọkùnrin náà bá níṣẹ́ lọ́wọ́, a jẹ́ pé owó tó ń gbà kò tó nǹkan.
7. Ọkùnrin náà kò jáde ilé ẹ̀kọ́ gíga.
8. Ọjọ́ orí rẹ̀ kò ju méjìdínlógún sí ọgbọ̀n lọ.
9. Bàbá tàbí ìyá ọkùnrin náà tàbí àwọn méjèèjì ń hùwà ipá sáwọn ọmọ nílé.
10. Gbogbo owó tó ń wọlé fún un kò tó nǹkan.
11. Àṣà ìbílẹ̀ ọkùnrin náà àti ìyàwó rẹ̀ yàtọ̀ síra.
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 7]
Ìwà ipá nínú ilé lè nípa burúkú lórí àwọn ọmọ
-
-
Ìrànwọ́ fún Àwọn Obìnrin Tí Ọkọ Wọn Ń LùJí!—2001 | November 8
-
-
Ìrànwọ́ fún Àwọn Obìnrin Tí Ọkọ Wọn Ń Lù
KÍ LA lè ṣe láti ran àwọn obìnrin tí ọkọ wọn ń lù lọ́wọ́? Lákọ̀ọ́kọ́, èèyàn gbọ́dọ̀ mọ ohun tójú wọn ń rí. Lọ́pọ̀ ìgbà, ọṣẹ́ tí ọkọ wọn ti ṣe wọ́n kọjá ti ara lásán. Wọ́n máa ń dẹ́rù ba àwọn obìnrin wọ̀nyí tí wọ́n á sì fẹnu ṣáátá wọn lọ́pọ̀ ìgbà, kí irú àwọn obìnrin bẹ́ẹ̀ lè rò pé àwọn kò já mọ́ nǹkankan pé àwọn ò sì ní olùrànlọ́wọ́.
Wo ti Roxana, tá a sọ̀rọ̀ rẹ̀ nínú àpilẹ̀kọ àkọ́kọ́. Nígbà míì, ọ̀rọ̀ ẹnu lọkọ rẹ̀ máa fi ń ṣe ohun ìjà. Roxana sọ pé: “Orúkọ tí kò yẹ ọmọ èèyàn ló máa ń pè mí. Ó máa ń sọ pé: ‘Ààbọ̀ ẹ̀kọ́ ló ń yọ ẹ lẹ́nu. Bá a bá yọwọ́ tèmi, ṣé o lè dá tọ́jú àwọn ọmọ ni? Ọ̀lẹ afàjò ni ọ́, ìyá lásán. Ṣé o rò pé ìjọba á jẹ́ kó o kó àwọn ọmọ tira bó o bá kọ̀ mí sílẹ̀ ni?’”
Ńṣe ni ọkọ Roxana máa ń fúnka mọ́ owó kí ó sáà lè jẹ́ òun nìkan lọ̀gá. Kò gbà kí ìyàwó rẹ̀ lo ọkọ̀ wọn, ìṣẹ́jú ìṣẹ́jú ló sì máa ń tẹlifóònù ìyàwó rẹ̀ nínú ilé kó lè mọ ohun tíyẹn ń ṣe. Tí obìnrin yìí bá sọ pé ohun báyìí ló dára lójú òun pẹ́nrẹ́n, ńṣe lọkọ rẹ̀ máa gbaná jẹ. Nítorí náà, Roxana kì í tiẹ̀ gbin pínkín pé báyìí ni nǹkan ṣe rí lára òun.
Gẹ́gẹ́ bá a ti lè rí i, ìṣòro ńlá gbáà ni ọ̀ràn fífi ìyà jẹ ìyàwó ẹni o. Láti ran irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́, o ní láti tẹ́tí bẹ̀lẹ̀jẹ́ sí wọn. Rántí pé ó máa ń nira gan-an lọ́pọ̀ ìgbà fún ẹni tójú rẹ̀ ń rí màbo yìí láti sọ gbogbo ohun tójú rẹ̀ ń rí. Ohun tí ìwọ gbọ́dọ̀ ní lọ́kàn láti ṣe ni pé kó o fún irú obìnrin bẹ́ẹ̀ lókun tí á fi kojú ìṣòro náà díẹ̀díẹ̀.
Àwọn obìnrin mìíràn tí ọkọ wọn ń lù ní láti kàn sí ìjọba fún ìrànlọ́wọ́. Nígbà mìíràn, bọ́ràn bá di ti ìjọba, bóyá táwọn ọlọ́pàá tiẹ̀ wá dá sí ọ̀ràn náà, ìyẹn lè jẹ́ kí ọkùnrin náà rí i pé ìwà tóun ń hù kò dára páàpáà. Bó ti wù kó rí, òótọ́ ni pé gbogbo kùrùkẹrẹ tí ọkùnrin náà ń ṣe pé òun fẹ́ yí padà lè wọ̀ ṣin-in bí atẹ́gùn bá ti fẹ́ sí ọ̀ràn náà.
Ṣé ó yẹ kí ìyàwó tí ọkọ rẹ̀ ń fìyà jẹ kó kúrò lọ́dọ̀ ọkọ rẹ̀? Bíbélì kò fi ọ̀rọ̀ pé kí ọkọ àti aya fi ara wọn sílẹ̀ ṣe ṣeréṣeré o. Àmọ́ ṣá, kò fi dandan lé e pé ìyàwó tí ọkọ rẹ̀ ń lù tó tiẹ̀ fẹ́ gbẹ̀mí rẹ̀ pàápàá gbọ́dọ̀ jókòó sọ́dọ̀ irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀. Kristẹni àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ ọ́ pé: “Bí ó bá lọ ní ti gidi, kí ó wà láìlọ́kọ, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ kí ó parí aáwọ̀ pẹ̀lú ọkọ rẹ̀.” (1 Kọ́ríńtì 7:10-16) Ìgbà tí Bíbélì kò kúkú fòfin dè é pé ọkọ àti aya kò lè pínyà bọ́ràn bá di kàráǹgídá, ìpinnu yòówù kí obìnrin kan ṣe bọ́ràn bá rí báyìí jẹ́ ti ara ẹni. (Gálátíà 6:5) Ẹnikẹ́ni kò gbọ́dọ̀ fúngun mọ́ obìnrin kan pe kí ó kó kúrò lọ́dọ̀ ọkọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ẹnikẹ́ni kò gbọ́dọ̀ sọ pé kí obìnrin kan dúró sọ́dọ̀ ọkọ rẹ̀ tí ìlera rẹ̀, ìwàláàyè rẹ̀, àti ipò tẹ̀mí obìnrin náà bá wà nínú ewu.
Ǹjẹ́ Àwọn Tó Ń Lu Ìyàwó Wọn Lè Yí Padà?
Títàpá sí ìlànà inú Bíbélì ni àṣà kí ọkùnrin máa lu ìyàwó rẹ̀. A kà á nínú ìwé Éfésù 4:29, 31, pé: “Kí àsọjáde jíjẹrà má ti ẹnu yín jáde . . . Kí ẹ mú gbogbo ìwà kíkorò onínú burúkú àti ìbínú àti ìrunú àti ìlọgun àti ọ̀rọ̀ èébú kúrò lọ́dọ̀ yín pa pọ̀ pẹ̀lú gbogbo ìwà búburú.”
Kò sí ọkọ tó máa sọ pé òun ń tẹ̀ lé Kristi táá lè fi gbogbo ẹnu sọ pé òun fẹ́ràn ìyàwó òun tó bá ń fìyà jẹ ẹ́. Kí ló máa jẹ́ àǹfààní gbogbo iṣẹ́ rere mìíràn tó bá ń ṣe nígbà tó jẹ́ pé ó ń fojú ìyàwó rẹ̀ rí màbo? “Aluni” kò tóótun fún àǹfààní àkànṣe èyíkéyìí nínú ìjọ Kristẹni. (1 Tímótì 3:3; 1 Kọ́ríńtì 13:1-3) Àní, ẹnikẹ́ni tó bá sọ pé Kristẹni lòun, tó sì ń bínú ní gbogbo ìgbà láìronúpìwàdà, lè di ẹni tá a yọ kúrò nínú ìjọ Kristẹni.—Gálátíà 5:19-21; 2 Jòhánù 9, 10.
Ǹjẹ́ àwọn ọkùnrin tí wọ́n burú lè yí ìwà wọn padà? Àwọn kan ti ṣe bẹ́ẹ̀. Àmọ́ bó ti sábàá máa ń rí, ọkùnrin kan tó ń fìyà jẹ ìyàwó rẹ̀ kò lè yí padà àyàfi (1) tó bá gbà pé nǹkan tóun ń ṣe kò dára, (2) tó bá wù ú láti yí padà, àti (3) tó bá wá ìrànlọ́wọ́. Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ti rí i pé Bíbélì lágbára gan-an láti yí èèyàn padà. Ọ̀pọ̀ àwọn tó fìfẹ́ hàn tí wọ́n sì ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì pẹ̀lú wọn ló ti wá nífẹ̀ẹ́ láti mú inú Ọlọ́run dùn. Àwọn tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì yìí kọ́ nípa Jèhófà Ọlọ́run pé “dájúdájú, ọkàn Rẹ̀ kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá nífẹ̀ẹ́ ìwà ipá.” (Sáàmù 11:5) Lóòótọ́, kì í kàn án ṣe pé kí ẹni tó ń lu ìyàwó rẹ̀ tẹ́lẹ̀ máà lù ú mọ́ ló túmọ̀ sí pé ó ti yí padà. Ó tún kan pé kí gbogbo ohun tó ń rò tó sì ń ṣe sí ìyàwó rẹ̀ yí padà.
Nígbà tí ọkùnrin kan bá bẹ̀rẹ̀ sí í gba ìmọ̀ Ọlọ́run, á mọ̀ pé òun kò gbọ́dọ̀ wo ìyàwó òun bí ẹrú, kàkà bẹ́ẹ̀ “olùrànlọ́wọ́” ni. Á mọ̀ pé kì í ṣe ẹni tí kò ní láárí ni ṣùgbọ́n ẹni tí òun gbọ́dọ̀ fi ‘ọlá’ fún. (Jẹ́nẹ́sísì 2:18; 1 Pétérù 3:7) Á tún kọ́ láti jẹ́ oníyọ̀ọ́nú àti pé ó yẹ kóun máa fetí sí ohun tí ìyàwó òun bá ní lọ́kàn. (Jẹ́nẹ́sísì 21:12; Oníwàásù 4:1) Ìtòlẹ́sẹẹsẹ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì táwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń ṣe ti ran ọ̀pọ̀ tọkọtaya lọ́wọ́. Kò sáyè fún bíbúmọ́ni tàbí àkóso oníwà ìkà nínú ìdílé Kristẹni.—Éfésù 5:25, 28, 29.
“Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run yè, ó sì ń sa agbára.” (Hébérù 4:12) Nítorí náà, ọgbọ́n tó wà nínú Bíbélì lè ran àwọn lọ́kọláya lọ́wọ́ láti gbé ohun tó jẹ́ ìṣòro wọn yẹ̀ wò fínnífínní á sì tún fún wọn ní ìgboyà láti kojú rẹ̀. Ohun tó tún ju ìyẹn lọ ni pé, ìrètí tó dájú tó sì ń tuni nínú wà nínú Bíbélì, ìyẹn nípa rírí ayé kan tí kò ti ní sí ìwà ipá, níbi tí Ọba ọ̀run ti Jèhófà yóò ti máa ṣàkóso lórí gbogbo ìran ènìyàn onígbọràn. Bíbélì sọ pé: “Òun yóò dá òtòṣì tí ń kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nídè, ẹni tí ìṣẹ́ ń ṣẹ́ pẹ̀lú, àti ẹnì yòówù tí kò ní olùrànlọ́wọ́. Yóò tún ọkàn wọn rà padà lọ́wọ́ ìnilára àti lọ́wọ́ ìwà ipá.”—Sáàmù 72:12, 14.
[Ìsọfúnni tá a pàfiyèsí sí ní ojú ìwé 12]
Kò sáyè fún bíbúmọ́ni tàbí àkóso oníwà ìkà nínú ìdílé Kristẹni
[Àpótí tó wà ní ojú ìwé 8]
Èrò Táwọn Kan Ní Kò Tọ̀nà O
• Àwọn obìnrin táwọn ọkọ wọn máa ń lù ló ń fà á.
Ọ̀pọ̀ àwọn ọkùnrin tó ń lu ìyàwó wọn ló sọ pé kì í ṣe ẹ̀bi àwọn, pé ìyàwó àwọn ló múnú bí àwọn. Kódà àwọn ọ̀rẹ́ wọn pàápàá lè gba ohun tí ọkọ náà sọ gbọ́ pé obìnrin náà ló ya pamí-n-kú aya, pé ìyẹn ló mú kí ọkọ máa fìyà jẹ ẹ́ nígbà gbogbo. Àmọ́ ńṣe ni wọ́n ń gbé ẹ̀bi fún aláre. Ká sòótọ́, àwọn ìyàwó tí ọkọ wọn ń lù yìí máa ń forí ṣe fọrùn ṣe láti tu ọkọ wọn lójú. Yàtọ̀ síyẹn gan-an, ìwà àìdáa gbáà ni kéèyàn máa fìyà jẹ ìyàwó rẹ̀. Ìwé The Batterer—A Psychological Profile sọ pé: “Àwọn ọkùnrin tí ilé ẹjọ́ ní kí wọ́n lọ gba ìtọ́jú kí wọ́n lè ṣíwọ́ lílu ìyàwó wọn jẹ́ àwọn tí ìwà ipá ti wọ̀ lẹ́wù. Wọ́n máa ń ṣe bẹ́ẹ̀ kí inú tó ń bí wọn àti ìsoríkọ́ wọn bàa lè lọ, òun ni wọ́n fi ń pa ìrònú rẹ́, òun ni wọ́n sì fi ń yanjú aáwọ̀. . . . Ọ̀pọ̀ ìgbà tiẹ̀ ni wọn kì í mọ̀ pé àwọn ni ọ̀dádá tó ń dá wàhálà sílẹ̀, wọn kì í sì í ka ìṣòro náà sí ohun bàbàrà.”
• Ọtí líle ló ń mú kí ọkùnrin máa lu ìyàwó rẹ̀.
Òótọ́ ni pé ìwà ipá àwọn ọkùnrin kan kúrò ní kèrémí nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í mutí. Àmọ́ ṣé ọtí líle ló wá yẹ ká bá wí? K. J. Wilson, kọ ọ́ nínú ìwé rẹ̀ When Violence Begins at Home pé: “Ọtí tí ẹni tó ń lu ìyàwó rẹ̀ mu yó á jẹ́ kó rí nǹkan parọ́ mọ́ pé òun ló jẹ́ kóun hùwà tí òun hù.” Ó tún sọ pé: “Ó dà bí ẹni pé nínú àwùjọ wa, ìwà ipá nínú ilé dùn ún gbọ́ sétí tó bá jẹ́ pé ẹni tó mutí yó ló hù ú. Obìnrin tí ọkọ rẹ̀ ń lù lè máà ka ọkọ rẹ̀ sí ẹni tó lè ṣe é léṣe, kàkà bẹ́ẹ̀ ó lè kà á sí pé ọtí ìmukúmu tó ń mu ló ń fà á.” Wilson wá sọ pé irú èrò bẹ́ẹ̀ lè jẹ́ kí obìnrin kan máa fojú síbi tí ọ̀nà kò sí pé “bí ọkùnrin náà bá lè jáwọ́ ọtí mímú báyìí, kò ní hu ìwà ipá mọ́.”
Ní báyìí, ọ̀pọ̀ àwọn olùwádìí ka ọtí mímu àti lílu ìyàwó ẹni sí ohun méjì tó yàtọ̀ síra wọn. Ó ṣe tán, èyí tó pọ̀ jù nínú àwọn ọkùnrin tó ń lo oògùn olóró ni kì í lu ìyàwó wọn. Àwọn òǹkọ̀wée When Men Batter Women sọ pé: “Ohun tó ń jẹ́ kí lílu ìyàwó ẹni máa bá a lọ ni pé, ẹni tó ń ṣe bẹ́ẹ̀ ń lò ó láti jẹ gàba lé ìyàwó rẹ̀ lórí, láti tẹ́ ẹ, àti láti fi halẹ̀ mọ́ ọn. . . . Ẹni tó ń lu ìyàwó rẹ̀ yìí kì í fi ọtí líle àti oògùn olóró ṣeré rárá. Àmọ́ àṣìṣe ńlá gbáà ló máa jẹ́ tá a bá rò pé ọtí líle àti oògùn olóró tó ń lò ló ń fa ìwà ipá yìí.”
• Bákan náà làwọn tó ń lu ìyàwó wọn ṣe ń hùwà ipá sí gbogbo èèyàn.
Ọkùnrin tó ń lu ìyàwó rẹ̀ sábàá máa ń hùwà ọmọlúwàbí sáwọn mìíràn. Ìwà rẹ̀ á wá yàtọ̀ pátápátá. Èyí ni kì í jẹ́ káwọn ọ̀rẹ́ wọn lè gbà pé lóòótọ́ ló ń lu ìyàwó rẹ̀. Àmọ́, òtítọ́ ibẹ̀ ni pé ńṣe lẹni tó ń lu ìyàwó rẹ̀ yìí ń mọ̀ọ́mọ̀ ṣe bẹ́ẹ̀ láti fi jẹ gàba lórí ìyàwó rẹ̀.
• Àwọn obìnrin kì í ké gbàjarè tí ọkọ wọn bá ń lù wọ́n.
Àfàìmọ̀ ni kò ní jẹ́ pé bí àwọn èèyàn ò ṣe lóye ipò irú obìnrin bẹ́ẹ̀ ló mú kí wọ́n lérò yìí, ẹni ẹlẹ́ni tí kò síbi tó máa sá gbà. Obìnrin tí ọkọ rẹ̀ ti lù yìí lè ní àwọn ọ̀rẹ́ tó lè gbà á sọ́dọ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan tàbí méjì, àmọ́ kí ló máa ṣe lẹ́yìn èyí? Àtiwá iṣẹ́, kó máa sanwó ilé, kó sì tún máa tọ́jú àwọn ọmọ lè di nǹkan tá á máa dà á lọ́kàn rú. Òfin sì lè má gbà á láyè láti kó àwọn ọmọ sá lọ. Àwọn kan tiẹ̀ ti sá lọ rí, àmọ́ ọkọ wọn wá wọn kàn ó sì mú wọn padà, yálà ní tipátipá tàbí lẹ́yìn tí ọkọ bẹ̀bẹ̀. Àwọn ọ̀rẹ́ tí ọ̀rọ̀ náà kò yé lè máa rò pé ńṣe ni irú àwọn obìnrin bẹ́ẹ̀ kò ké gbàjarè nítorí ìyà tí ọkọ wọn fi ń jẹ wọ́n.
-
-
“Bí Àlá Ló Máa Ń Rí Lójú Mi Nígbà Míì!”Jí!—2001 | November 8
-
-
“Bí Àlá Ló Máa Ń Rí Lójú Mi Nígbà Míì!”
Lourdes ń wo bí ìlú ṣe rí lọ láti ojú fèrèsé ilé rẹ̀, ó fọwọ́ bo ẹnu rẹ̀ tó ń gbọ̀n pẹ̀pẹ̀. Ọmọ orílẹ̀-èdè Látìn-Amẹ́ríkà ni, ó lé ní ogún ọdún tó fi jẹ palaba ìyà lọ́wọ́ ọkọ rẹ̀ Alfredo, tó jẹ́ oníwà ipá. Alfredo mà yí padà o. Síbẹ̀, ẹnu Lourdes kò lè sọ ohun tójú rẹ̀ kàn àti palaba ìyà tó fara dà.
Lourdes fohùn jẹ́jẹ́ sọ pé: “Ọ̀sẹ̀ méjì péré lẹ́yìn tá a fẹ́ra wa lọ̀rọ̀ náà bẹ̀rẹ̀. Ìgbà kan wà tó fi ẹ̀ṣẹ́ yọ eyín mi méjì. Lákòókò mìíràn, ó ju ẹ̀ṣẹ́ sí mi, àmọ́ mo yẹ̀ ẹ́, ó sì fọwọ́ gbá àpótí aṣọ dá lu. Àmọ́ àwọn orúkọ burúkú tó máa ń pè mí ló dùn mí jù. Ó máa ń pè mí ní ‘akídanidání’ ó sì máa ń hùwà sí mi bí ẹni pé mi ò tiẹ̀ ní ọpọlọ. Mo fẹ́ kó jáde, àmọ́ báwo ni mo ṣe lè kó jáde pẹ̀lú ọmọ mẹ́ta?”
Alfredo rọra gbé ọwọ́ lé èjìká Lourdes. Ó sì sọ pé: “Ọ̀gá kan tó mọṣẹ́ dunjú ni mí. Ńṣe ló dà bí ẹni pé wọ́n fi ìwọ̀sí lọ̀ mí nígbà tí ilé ẹjọ́ ní kí n wá, tó sì pa á láṣẹ fún mi pé mi ò gbọ́dọ̀ tún lu ìyàwó mi mọ́. Mo gbìyànjú láti yí padà, àmọ́ kò pẹ́ tí mo tún bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ohun kan náà.”
Báwo ni nǹkan ṣe wá yí padà? Lourdes, tára rẹ̀ ti wá balẹ̀ báyìí ṣàlàyé pé: “Obìnrin kan tó wà nílé ìtajà ní òpópó wa jẹ́ ọ̀kan lára àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà. Ó sọ pé òun á ràn mí lọ́wọ́ láti lóye Bíbélì. Mo kẹ́kọ̀ọ́ pé Jèhófà Ọlọ́run kò fọ̀rọ̀ àwọn obìnrin ṣeré rárá. Mo bẹ̀rẹ̀ sí lọ sí ìpàdé àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà, bó tilẹ̀ jẹ́ pé Alfredo kọ́kọ́ gbaná jẹ nítorí èyí. Ìrírí tuntun ló jẹ́ fún mi láti wà pẹ̀lú àwọn ọ̀rẹ́ ní Gbọ̀ngàn Ìjọba. Kàyéfì gbáà ló jẹ́ fún mi láti mọ̀ pé mo lè dá ní ìgbàgbọ́ tèmi, kí n sọ ọ́ jáde bó bá ṣe wù mí, kí n tiẹ̀ tún fi kọ́ àwọn ẹlòmíràn pẹ̀lú. Mo wá rí i pé Ọlọ́run kà mí sí. Èyí fún mi ní ìgboyà.
“Ìyípadà kan ṣẹlẹ̀ tí mi ò lè gbàgbé láé. Alfredo ṣì ń lọ sí Máàsì Kátólíìkì ní ọjọọjọ́ Sunday, ó sì yarí nítorí ohun tí mò ń ṣe pẹ̀lú àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà. Mo tẹjú mọ́ ọn, mo sì fohùn pẹ̀lẹ́ sọ pé: ‘Alfredo, ohun tó o ń rò kọ́ lèmi ń rò o.’ Kò mà gbá mi lẹ́ṣẹ̀ẹ́ o! Kò pẹ́ sígbà yẹn ni mo ṣe ìrìbọmi, kò sì tí ì tún lù mí fún odindi ọdún márùn-ún láti ìgbà yẹn.”
Àmọ́ kékeré ni ìyípadà ti mo ṣì rí. Alfredo ṣàlàyé pé: “Lẹ́yìn nǹkan bí ọdún mẹ́ta tí Lourdes ṣèrìbọmi, ẹnì kan tá a jọ ń ṣiṣẹ́ tó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà pè mí wálé rẹ̀, ó sì ṣàlàyé àwọn nǹkan tó fà mí lọ́kàn mọ́ra fún mi látinú Bíbélì. Mo bẹ̀rẹ̀ sí kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ́dọ̀ rẹ̀ láìsọ fún ìyàwó mi. Láìpẹ́, mo bẹ̀rẹ̀ sí tẹ̀ lé Lourdes lọ sáwọn ìpàdé. Èyí tó pọ̀ lára àwọn àsọyé tí mo gbọ́ níbẹ̀ ló dá lórí ìgbésí ayé ìdílé, èyí sì máa ń mú kí ojú tì mí lọ́pọ̀ ìgbà.”
Ó ya Alfredo lẹ́nu láti rí bí àwọn tó wà nínú ìjọ, tó fi dórí àwọn ọkùnrin ṣe ń gbálẹ̀ lẹ́yìn ìpàdé. Tó bá lọ kí wọn nílé, ó máa ń rí bí àwọn ọkọ ṣe máa ń bá ìyàwó wọn fọ abọ́. Àwọn nǹkan pẹ́ẹ́pẹ̀ẹ̀pẹ́ yìí jẹ́ kí Alfredo rí i béèyàn ṣe ń fi ìfẹ́ tòótọ́ hàn.
Kò pẹ́ lẹ́yìn náà ni Alfredo ṣèrìbọmi, ní báyìí, òun àti ìyàwó rẹ̀ ń sìn bí òjíṣẹ́ alákòókò kíkún. Lourdes sọ pé: “Ọ̀pọ̀ ìgbà ló máa ń bá mi palẹ̀ tábìlì mọ́ lẹ́yìn oúnjẹ ó sì máa ń bá mi tẹ́ bẹ́ẹ̀dì. Ó máa ń yìn mí pé mo mọ oúnjẹ sè, ó sì máa ń fún mi láyè láti sọ ohun tó bá wù mí, bí irú orin tí mo fẹ́ gbọ́ tàbí irú àwọn ohun wo ni màá fẹ́ kí á rà sílé. Tẹ́lẹ̀, Alfredo kò jẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀! Láìpẹ́ yìí, ó ra òdòdó fún mi fún ìgbà àkọ́kọ́. Bí àlá ló máa ń rí lójú mi nígbà míì!”
-