ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • “Àánú Ṣe É”
    “Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”
    • ORÍ KẸẸ̀Ẹ́DÓGÚN

      “Àánú Ṣe É”

      Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 151

      “Olúwa, jẹ́ kí ojú wa là”

      1-3. (a) Kí ni Jésù ṣe nígbà táwọn afọ́jú méjì tó ń ṣagbe bẹ̀ ẹ́ pé kò ran àwọn lọ́wọ́? (b) Kí ni ìtumọ̀ gbólóhùn náà ‘àánú ṣe é’? (Wo àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé.)

      ÀWỌN ọkùnrin afọ́jú méjì kan jókòó sí ẹ̀bá ọ̀nà nítòsí Jẹ́ríkò. Ojoojúmọ́ ni wọ́n máa ń wá síbẹ̀, wọ́n á wá ibi tí wọ́n rò pé ọ̀pọ̀ èèyàn á máa gbà kọjá, wọ́n á sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣagbe níbẹ̀. Àmọ́ lọ́tẹ̀ yìí, nǹkan kan máa tó ṣẹlẹ̀ sí wọn tó máa yí ìgbésí ayé wọn padà pátápátá.

      2 Lójijì, àwọn alágbe yẹn gbọ́ ariwo. Nítorí pé wọn ò lè rí ohun tó ń lọ, ọ̀kan lára wọn béèrè ohun tó ń ṣẹlẹ̀, àwọn èèyàn sì dá a lóhùn pé: “Jésù ará Násárétì ni ó ń kọjá lọ!” Ìgbà ìkẹyìn rèé tí Jésù ń lọ sí Jerúsálẹ́mù. Ṣùgbọ́n òun nìkan kọ́ ló ń lọ; ọ̀pọ̀ èrò ló ń wọ́ tẹ̀ lé e. Kí làwọn alágbe náà gbọ́ pé Jésù ló ń kọjá sí, ńṣe ni wọ́n ṣe ohun kan tó lè bí àwọn èèyàn nínú. Ohun tí wọ́n ṣe náà sì ni ariwo tí wọ́n ń pa pé: “Olúwa, ṣàánú fún wa, Ọmọkùnrin Dáfídì!” Ìyẹn bí àwọn ogunlọ́gọ̀ náà nínú, wọ́n sì ní káwọn alágbe yẹn panu mọ́, ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ò gbọ́. Wọ́n kọ̀ láti panu mọ́.

      3 Pẹ̀lú bí ariwo ogunlọ́gọ̀ náà ṣe ròkè tó, Jésù ṣì gbọ́ igbe àwọn alágbe náà. Kí ló máa ṣe o? Ọ̀pọ̀ nǹkan ló gbé sọ́kàn. Nǹkan bí ọ̀sẹ̀ kan péré ló kù kó lò láyé. Ó mọ̀ pé dẹndẹ ìyà àti ikú oró ń dúró de òun ní Jerúsálẹ́mù. Síbẹ̀ kò tìtorí ìyẹn fi gbígbọ́ ṣaláìgbọ́ bí àwọn alágbe yẹn ò ṣe yéé bẹ̀ ẹ́. Ó tẹsẹ̀ dúró díẹ̀, ó wá ní kí wọ́n mú àwọn alágbe tó ń kígbe yẹn sún mọ́ òun. Àwọn alágbe náà bẹ̀bẹ̀ pé: “Olúwa, jẹ́ kí ojú wa là.” “Bí àánú ti ṣe é,” ó fọwọ́ kan ojú wọn, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ríran.a Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ni wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í tẹ̀ lé Jésù.—Lúùkù 18:35-43; Mátíù 20:29-34.

      4. Báwo ni Jésù ṣe mú àsọtẹ́lẹ̀ tó sọ pé ó máa “káàánú ẹni rírẹlẹ̀” ṣẹ?

      4 Kì í ṣe ìgbà kan ṣoṣo tí Jésù fi àánú hàn nìyẹn. Lọ́pọ̀ ìgbà àti lónírúurú ipò, ọ̀rọ̀ àwọn èèyàn dun Jésù dọ́kàn débi tó fi ṣàánú fún wọn. Bíbélì tiẹ̀ sọ tẹ́lẹ̀ pé ó máa “káàánú ẹni rírẹlẹ̀.” (Sáàmù 72:13) Bí àwọn àsọtẹ́lẹ̀ yẹn ṣe sọ gẹ́lẹ́ ni Jésù ṣe, ó máa ń kíyè sí ohun tó ń da àwọn ẹlòmíì láàmú. Ó máa ń dìídì ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ kí wọ́n tó kọnu ìrànlọ́wọ́ sí i. Ìyọ́nú tó ní sáwọn èèyàn wà lára ohun tó ń mú un wàásù. Ẹ jẹ́ ká wo bí àwọn ìwé Ìhìn Rere ṣe jẹ́ ká rí bí àwọn ọ̀rọ̀ tó sọ àtàwọn ohun tó ṣe ṣe fi hàn pé ẹlẹ́yinjú àánú ni, ká sì rí báwa náà ṣe lè máa firú ìyọ́nú bẹ́ẹ̀ hàn.

      Bó Ṣe Máa Ń Gba Tàwọn Ẹlòmíì Rò

      5, 6. Àpẹẹrẹ wo ló jẹ́ ká mọ̀ pé Jésù máa ń fọ̀rọ̀ àwọn ẹlòmíì ro ara rẹ̀ wò?

      5 Jésù jẹ́ ẹnì kan tó máa ń fọ̀ràn ro ara rẹ̀ wò gan-an. Ó máa ń mọ bí ìṣòro àwọn èèyàn ṣe rí lára wọn, ó sì máa ń bá wọn kẹ́dùn. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ohun tó ń ṣe wọ́n yẹn kọ́ ló ti ṣeé rí, síbẹ̀ nínú ọkàn rẹ̀ lọ́hùn-ún, ó mọ bí ìrora yẹn ṣe lè rí lára. (Hébérù 4:15) Nígbà tó wo obìnrin tó ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún ọdún méjìlá sàn, ó pe àìsàn náà ní “àìsàn burúkú,” èyí tó túmọ̀ sí pé ó mọ ìnira àti ìpọ́njú tí àìsàn yẹn ti kó bá obìnrin náà. (Máàkù 5:25-34) Nígbà tó rí Màríà àtàwọn tó ń ṣọ̀fọ̀ nítorí ikú Lásárù, ìbànújẹ́ tó bá wọn dùn ún wọra débi tí kò fi lè mú un mọ́ra mọ́. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó mọ̀ pé òun máa lọ jí i dìde, síbẹ̀ ó dùn ún gan-an débi tó fi da omijé lójú.—Jòhánù 11:33, 35.

      6 Ìgbà kan tún wà tí adẹ́tẹ̀ kan tọ Jésù wá tó sì bẹ̀ ẹ́ pé: “Bí ìwọ bá sáà ti fẹ́ bẹ́ẹ̀, ìwọ lè mú kí èmi mọ́.” Báwo ni Jésù tó jẹ́ ẹni pípé tí ò ṣàìsàn rí ṣe fèsì? Ńṣe ni àánú adẹ́tẹ̀ yẹn ṣe é. Nítòótọ́, “àánú ṣe é.” (Máàkù 1:40-42) Ó sì ṣe ohun àrà kan. Ó mọ̀ dáadáa pé aláìmọ́ làwọn adẹ́tẹ̀ lábẹ́ Òfin Mósè àti pé wọn ò gbọ́dọ̀ wá sáàárín àwọn èèyàn. (Léfítíkù 13:45, 46) Jésù ní agbára tó fi lè mú ọkùnrin yìí lára dá láìfi ọwọ́ kàn án. (Mátíù 8:5-13) Síbẹ̀, ó pinnu láti nawọ́ sí adẹ́tẹ̀ náà, ó fọwọ́ kàn án, ó sì sọ pé: “Mo fẹ́ bẹ́ẹ̀. Kí ìwọ mọ́.” Lójú ẹsẹ, ẹ̀tẹ̀ yẹn dàwátì. Àbí ẹ ò rí i pé Jésù máa ń lo ìyọ́nú nípa fífi ọ̀ràn ro ara rẹ̀ wò!

      Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 154

      Máa fi “ìmọ̀lára fún ọmọnìkejì hàn”

      7. Kí ló lè ràn wá lọ́wọ́ láti ní ìyọ́nú, ọ̀nà wo la sì lè gbà fi hàn pé oníyọ̀ọ́nú èèyàn ni wá?

      7 Ó yẹ káwa Kristẹni máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù nínú fífi ọ̀rọ̀ àwọn ẹlòmíì ro ara wa wò. Bíbélì rọ̀ wá pé ká máa fi “ìmọ̀lára fún ọmọnìkejì hàn.”b (1 Pétérù 3:8) Ó lè má rọrùn láti mọ bó ṣe ń ṣe àwọn tí àìsàn líle ń bá fínra tàbí àwọn tí wọ́n ní ìsoríkọ́, pàápàá bí irú rẹ̀ ò bá tíì ṣe wá rí. Máa rántí pé kò dìgbà téèyàn bá nírú ìṣòro tẹ́nì kan ní kéèyàn tó lè káàánú irú ẹni bẹ́ẹ̀. Jésù fọ̀rọ̀ àwọn aláìsàn ro ara ẹ̀ wò, bẹ́ẹ̀ sì rèé òun ò ṣàìsàn rí. Báwo làwa náà ṣe lè wá kọ́ bá a ṣe máa fọ̀rọ̀ àwọn èèyàn ro ara wa wò? A lè ṣe bẹ́ẹ̀ nípa fífetísílẹ̀ dáadáa nígbà táwọn tójú ń pọ́n bá ń sọ ohun tó wà lọ́kàn wọn àti ohun tó ń ṣe wọ́n. A lè bi ara wa pé, ‘Bó bá jẹ́ pé èmi ni mo nírú ìṣòro yìí, kí ni màá ṣe?’ (1 Kọ́ríńtì 12:26) Bá a bá jẹ́ ẹni tó tètè ń kíyè sí ìṣesí àwọn èèyàn, ó máa rọrùn fún wa láti “máa sọ̀rọ̀ ìtùnú fún àwọn ọkàn tí ó soríkọ́.” (1 Tẹsalóníkà 5:14) Nígbà míì, tá a bá fi ọ̀rọ̀ àwọn èèyàn ro ara wa wò, omijé á gbọ̀n wá, á ṣe wá kọjá ká kàn máa sọ̀rọ̀. Róòmù 12:15 sọ pé: “Ẹ máa sunkún pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ń sunkún.”

      8, 9. Báwo ni Jésù ṣe ń fi ìgbatẹnirò hàn fáwọn ẹlòmíì?

      8 Jésù máa ń gba tàwọn ẹlòmíì rò, ó sì máa ń ṣe ohun to fi hàn bẹ́ẹ̀. Wàá rántí ìgbà kan tí wọ́n mú ọ̀gbẹ́ni tó dití tí kò sì lè sọ̀rọ̀ dáadáa wá sọ́dọ̀ rẹ̀. Nígbà tó kíyè sí i pé ara ń ti ọ̀gbẹ́ni yẹn, ó ṣe ohun àrà ọ̀tọ̀ kan tí kì í sábà ṣe bó bá ń wo àwọn èèyàn sàn. Ó mú ọ̀gbẹ́ni yẹn “lọ kúrò lọ́dọ̀ ogunlọ́gọ̀ náà.” Ní òun nìkan, níbi táwọn èèyàn ò ti ní máa wo ohun tó ń ṣẹlẹ̀ ló ti wo ọkùnrin yẹn sàn.—Máàkù 7:31-35.

      9 Ohun tó jọ ìyẹn náà ni Jésù ṣe nígbà táwọn èèyàn mú ọkùnrin afọ́jú kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀ pé kó wò ó sàn. Jésù “di ọwọ́ ọkùnrin afọ́jú náà mú,” ó sì “mú un jáde sẹ́yìn òde abúlé náà.” Ó bẹ̀rẹ̀ sí í wo ọkùnrin náà sàn díẹ̀ díẹ̀. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ńṣe ló ṣe báyẹn torí kí ọpọlọ ọkùnrin náà bàa lè gba àwọn ohun tójú rẹ̀ á rí, títí kan onírúurú ohun tó wà nínú ayé tí oòrùn tàn rekete sí. (Máàkù 8:22-26) Ìgbatẹnirò tí Jésù lò yìí mà ga o!

      10. Àwọn ọ̀nà wo la lè gbà fi hàn pé à ń ro bọ́ràn ṣe máa rí lára àwọn ẹlòmíì?

      10 Báwa náà bá máa jẹ́ ọmọlẹ́yìn Jésù, àfi ká yáa máa ro bọ́ràn ṣe máa ń rí lára àwọn ẹlòmíì. Nítorí náà, a gbọ́dọ̀ máa ṣọ́ra nípa ọ̀rọ̀ ẹnu wa, ká máa rántí pé lílo ahọ́n wa láìkíyèsára lè mú ká kó ìbànújẹ́ bá àwọn ẹlòmíì. (Òwe 12:18; 18:21) Kòbákùngbé ọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ èébú àti sísọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn kì í ṣe àṣà àwọn Kristẹni tí ò fẹ́ ba àwọn ẹlòmíì lọ́kàn jẹ́. (Éfésù 4:31) Báwo lẹ̀yin alàgbà ṣe lè fi hàn pé ẹ̀ ń ro bọ́ràn ṣe ń rí lára àwọn ẹlòmíì? Nígbà tẹ́ ẹ bá ń gbani nímọ̀ràn, ẹ máa sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ohùn tútù, kẹ́ ẹ fọ̀wọ̀ ẹni náà wọ̀ ọ́. (Gálátíà 6:1) Báwo lẹ̀yin òbí ṣe lè fi ìgbatẹnirò hàn fáwọn ọmọ yín? Tẹ́ ẹ bá ń bá ọmọ yín wí, ẹ rí i pé ìbáwí tẹ́ ẹ bá máa fún un kò ní kàn án lábùkù.—Kólósè 3:21.

      Bó O Ṣe Lè Lo Ìdánúṣe Láti Ran Àwọn Ẹlòmíì Lọ́wọ́

      11, 12. Àwọn àkọsílẹ̀ Bíbélì wo ló fi hàn pé Jésù kì í dúró dìgbà tí wọ́n bá sọ fún un kó tó fi ìyọ́nú hàn sáwọn ẹlòmíì?

      11 Jésù kì í dúró dìgbà tí wọ́n bá pè é kó tó ṣe ohun táwọn èèyàn nílò fún wọn. Ó ṣe tán, ìyọ́nú kì í ṣe ànímọ́ téèyàn á kàn fẹnu lásán sọ pé òun ní, kàkà bẹ́ẹ̀ ànímọ́ tó máa ń mú ká ṣe nǹkan kan láti ran ẹlòmíì lọ́wọ́ ni. Abájọ tí ìyọ́nú fi mú kí Jésù dìídì fẹ́ ran àwọn ẹlòmíì lọ́wọ́ láìṣe pé wọ́n bẹ̀ ẹ́. Bí àpẹẹrẹ, nígbà kan tí ogunlọ́gọ̀ wà lọ́dọ̀ rẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta, láìjẹ-láìmu, ẹnì kan ò ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ fún Jésù pé ebi ti ń pa wọ́n tàbí pé kó ṣe nǹkan kan nípa rẹ̀. Àkọsílẹ̀ náà sọ pé: “Jésù pe àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ wá sọ́dọ̀ ara rẹ̀, ó sì wí pé: ‘Àánú ogunlọ́gọ̀ náà ń ṣe mí, nítorí pé ó ti di ọjọ́ mẹ́ta báyìí tí wọ́n ti wà pẹ̀lú mi, wọn kò sì ní nǹkan kan láti jẹ; èmi kò sì fẹ́ rán wọn lọ ní gbígbààwẹ̀. Ó ṣeé ṣe kí okun wọn tán ní ojú ọ̀nà.’” Lẹ́yìn náà, láìjẹ́ pé ẹnì kan sọ fún un, òun fúnra rẹ̀ pinnu, ó sì bọ́ ogunlọ́gọ̀ náà lọ́nà ìyanu.—Mátíù 15:32-38.

      12 Jẹ́ ká gbé àkọsílẹ̀ míì yẹ̀ wò. Lọ́dún 31 Sànmánì Kristẹni, nígbà tí Jésù sún mọ́ ìlú Náínì, ó rí ohun ìbànújẹ́ kan tó ṣẹlẹ̀. Àwọn kan ń gbókùú jáde kúrò nílùú náà, ó sì ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ibojì kan tó wà lórí òkè nítòsí ni wọ́n fẹ́ lọ sin “ọmọkùnrin bíbí kan ṣoṣo” tí “opó” kan báyìí ní sí. Wo bí ìbànújẹ́ tó gba ọkàn opó yẹn á ṣe pọ̀ tó? Ọmọ kan ṣoṣo tó ní ló fẹ́ lọ gbé sin yẹn, kò sì sí ọkọ tí wọ́n lè jọ máa tura wọn nínú. Láàárín gbogbo àwọn èèyàn náà, Jésù “tajú kán rí” opó tó ti di aláìlọ́mọ yìí. Ohun tó rí yìí dùn ún dọ́kàn, àní sẹ́, “àánú rẹ̀ ṣe é.” Kò dúró dìgbà tẹ́nì kan bá wá bẹ̀ ẹ́ pé kó wá nǹkan kan ṣe sí ìṣòro náà. Ìyọ́nú tó wà lọ́kàn rẹ̀ ló mú kó dìídì fẹ́ ṣèrànlọ́wọ́. Ó sì “sún mọ́ ọn, ó sì fọwọ́ kan agà ìgbókùú náà,” ó jí ọ̀dọ́kùnrin náà dìde. Kí ló wá ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn náà? Jésù ò tìtorí ìyẹn sọ pé kí ọ̀dọ́kùnrin yẹn wá dara pọ̀ mọ́ Òun àti ogunlọ́gọ̀ yẹn nínú ìrìn àjò wọn o. Dípò ìyẹn, ńṣe ni Jésù “fi í fún ìyá rẹ̀,” ó padà sọ wọ́n di ìdílé, èyí jẹ́ kí opó yẹn ní ẹni táá máa bójú tó o.—Lúùkù 7:11-15.

      Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 157

      Má ṣe dúró dìgbà tí wọ́n bá wá bẹ̀ ọ́ kó o tó ṣèrànwọ́ fáwọn tó nílò ìrànlọ́wọ́

      13. Báwo la ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù nínú ṣíṣe ohun tó yẹ láti ran ẹni tó wà nínú ìṣòro lọ́wọ́, láìdúró dìgbà tí wọ́n bá tó bẹ̀ wá?

      13 Báwo la ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù? Òótọ́ ni pé àwa ò lè pèsè oúnjẹ lọ́nà ìyanu, a ò sì lè jí òkú dìde. Àmọ́ a lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù nígbà tá a bá dìídì ṣèrànwọ́ fáwọn ẹlòmíì, láìdúró dìgbà tí wọ́n bá tó ṣẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ̀ wá. Ọrọ̀ ajé lè dẹnu kọlẹ̀ fún onígbàgbọ́ kan bíi tiwa tàbí kí iṣẹ́ bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀. (1 Jòhánù 3:17) Ó ṣeé ṣe kí ilé opó kan nílò àtúnṣe lójú méjèèjì. (Jákọ́bù 1:27) A lè mọ ìdílé kan tí ọ̀fọ̀ ṣẹ̀ tí wọ́n sì nílò ìtùnú tàbí tí wọ́n nílò àwọn nǹkan tara míì. (1 Tẹsalóníkà 5:11) Tó bá di pé àwọn ará wa níṣòro, a ò ní láti dúró dìgbà tẹ́nì kan bá ní ká ṣèrànwọ́ ká tó ṣe é. (Òwe 3:27) Ìyọ́nú tá a ní sáwọn èèyàn ló máa jẹ́ ká lè ràn wọ́n lọ́wọ́ bá a bá ṣe lè ṣe tó láìjẹ́ pé wọ́n bẹ̀ wá. Má gbàgbé pé ìrànlọ́wọ́ tá a bá ṣe bó ṣe wù kó kéré tó tàbí ọ̀rọ̀ ìtùnú tá a bá sọ látọkànwá fẹ́nì kan lè fi hàn pé oníyọ̀ọ́nú èèyàn ni wá.—Kólósè 3:12.

      Ìyọ́nú Ló Mú Kó Wàásù

      14. Kí nìdí tí Jésù fi ka iṣẹ́ wíwàásù ìhìn rere sì pàtàkì tó bẹ́ẹ̀?

      14 Bá a ṣe rí i ní Ìsọ̀rí 2 nínú ìwé yìí, Jésù fi àpẹẹrẹ tó ta yọ lélẹ̀ fún wa nínú wíwàásù ìhìn rere. Ó ní: “Èmi gbọ́dọ̀ polongo ìhìn rere ìjọba Ọlọ́run fún àwọn ìlú ńlá mìíràn pẹ̀lú, nítorí pé tìtorí èyí ni a ṣe rán mi jáde.” (Lúùkù 4:43) Kí nìdí tó fi ka iṣẹ́ yìí sí pàtàkì tó bẹ́ẹ̀? Ìdí ni pé ó nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run. Àmọ́ nǹkan míì wà: Jíjẹ́ tó jẹ́ ẹlẹ́yinjú àánú máa ń jẹ́ kó lè ṣe ohun tó máa pòùngbẹ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tó ń gbẹ àwọn èèyàn. Nínú gbogbo ọ̀nà tó ti fi ìyọ́nú hàn, kò séyìí tó ṣe pàtàkì tó bó ṣe bọ́ àwọn tébi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń pa. Ẹ jẹ́ ká gbé méjì yẹ̀ wò lára ìṣẹ̀lẹ̀ tó jẹ́ ká rí ojú tí Jésù fi ń wo àwọn tó ń wàásù fún. Bá a ṣe ń ṣàgbéyẹ̀wò yìí, á ràn wá lọ́wọ́ láti yẹ ara wa wò láti mọ ohun tó ń mú káwa náà máa ṣiṣẹ́ ìwàásù.

      15, 16. Ṣàpèjúwe ìṣẹ̀lẹ̀ méjì tó jẹ́ ká mọ ojú tí Jésù fi ń wo àwọn tó ń wàásù fún.

      15 Lọ́dún 31 Sànmánì Kristẹni, lẹ́yìn nǹkan bí ọdún méjì tí Jésù ti ṣiṣẹ́ àṣekára lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù, ó wá tẹ̀ síwájú láti “mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n nínú ìrìn àjò ìbẹ̀wò sí gbogbo àwọn ìlú ńlá àti àwọn abúlé” Gálílì. Ohun tó rí wọ̀ ọ́ lọ́kàn. Àpọ́sítélì Mátíù sọ pé: “Nígbà tí ó rí àwọn ogunlọ́gọ̀, àánú wọn ṣe é, nítorí a bó wọn láwọ, a sì fọ́n wọn ká bí àwọn àgùntàn tí kò ní olùṣọ́ àgùntàn.” (Mátíù 9:35, 36) Jésù fọ̀rọ̀ àwọn mẹ̀kúnnù ro ara rẹ̀ wò. Ó máa ń tètè mọ̀ pé ìmọ̀ tí wọ́n ní nípa Ọlọ́run ò tó. Ó mọ̀ pé àwọn tó yẹ kó bójú tó wọn gan-an, ìyẹn àwọn aṣáájú-ìsìn, ló ń ṣàìdáa sí wọn tí wọn ò sì bìkítà fún wọn. Nítorí bí ìyọ́nú tí Jésù ní fún wọn ṣe pọ̀ tó, ó sapá gidigidi láti lè rí i pé òun wàásù ìhìn rere tó ń fúnni ní ìrètí fún wọn. Kò sí nǹkan míì tí wọ́n nílò tó tó ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run.

      16 Ohun tó jọ èyí wáyé ní oṣù mélòó kan lẹ́yìn náà nígbà tí Àjọ Ìrékọjá ti ọdún 32 Sànmánì Kristẹni kù fẹ́ẹ́rẹ́fẹ́. Lákòókò tá à ń sọ yìí, ńṣe ni Jésù àtàwọn àpọ́sítélì rẹ̀ wọkọ̀ ojú omi kọjá lórí Òkun Gálílì láti lè wá ibi tó dákẹ́ rọ́rọ́ kí wọ́n lè sinmi. Ṣùgbọ́n ogunlọ́gọ̀ ti sáré dé etíkun kí ọkọ ojú omi tí Jésù wà nínú rẹ̀ tó débẹ̀. Kí ni Jésù ṣe? “Ní jíjáde, ó rí ogunlọ́gọ̀ ńlá, ṣùgbọ́n àánú wọ́n ṣe é, nítorí wọ́n dà bí àwọn àgùntàn tí kò ní olùṣọ́ àgùntàn. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ wọn ní ohun púpọ̀.” (Máàkù 6:31-34) Lẹ́ẹ̀kan sí i, “àánú wọ́n ṣe é” nítorí bí òùngbẹ tẹ̀mí ṣe ń gbẹ àwọn èèyàn náà. Bí “àwọn àgùntàn tí kò ní olùṣọ́ àgùntàn,” kò sẹ́ni táá máa fún àwọn èèyàn yìí ní oúnjẹ tẹ̀mí, tó sì jẹ́ pé àwọn fúnra wọn ni wọ́n ní láti mọ àtiṣe ara wọn. Ìyọ́nú tí Jésù ní ló sún un láti máa wàásù kì í ṣe torí pé ó di dandan kó wàásù.

      Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 159

      Jẹ́ kí àánú máa sún ọ láti wàásù

      17, 18. (a) Kí ló ń jẹ́ ká máa wàásù fáwọn èèyàn? (b) Báwo la ṣe lè máa fi ìyọ́nú hàn sáwọn ẹlòmíì?

      17 Kí ló jẹ́ káwa tá a jẹ́ ọmọlẹ́yìn Jésù máa wàásù? Bá a ṣe rí i ní Orí 9 nínú ìwé yìí, a ní iṣẹ́ kan níkàáwọ́ wa tó jẹ́ ojúṣe wa, ìyẹn ni iṣẹ́ wíwàásù àti iṣẹ́ sísọ àwọn èèyàn di ọmọlẹ́yìn. (Mátíù 28:19, 20; 1 Kọ́ríńtì 9:16) Ṣùgbọ́n kì í ṣe torí pé iṣẹ́ ìwàásù pọn dandan tàbí pó jẹ́ ojúṣe wa nìkan la fi ní láti máa wàásù o. Ìfẹ́ tá a ní fún Jèhófà lohun tó ṣe pàtàkì jù lọ tó yẹ kó mú ká máa lọ wàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run. Bí àánú àwọn tí kì í ṣe onígbàgbọ́ bíi tiwa ṣe ń ṣe wá tún wà lára ohun tó ń jẹ́ ká máa wàásù. (Máàkù 12:28-31) Báwo la ṣe wá lè máa fi ìyọ́nú hàn sáwọn èèyàn?

      18 Ó pọn dandan ká máa wo àwọn èèyàn bí Jésù ṣe ń wò wọ́n, ó rí i pé wọ́n ti “bó wọn láwọ,” wọ́n “sì fọ́n wọn ká bí àwọn àgùntàn tí kò ní olùṣọ́ àgùntàn.” Wo bó ṣe máa rí lára rẹ bó o bá rí ọ̀dọ́ àgùntàn kan tó ti sọ nù sínú igbó, tí ò sì mọ̀nà àbáyọ. Òùngbẹ á ti máa gbẹ ọ̀dọ́ àgùntàn yẹn, ebi á sì ti máa pa á torí kò sí olùṣọ́ àgùntàn tó máa mú un lọ síbi tí koríko tútù wà àti ibi tó ti lè rí omi mu. Ṣé àánú ọ̀dọ́ àgùntàn yẹn ò ní ṣe ọ́? Ṣé kò ní wù ọ́ láti ṣe gbogbo ohun tó o lè ṣe láti fún ọ̀dọ́ àgùntàn yẹn ní oúnjẹ àti omi? Ọ̀dọ́ àgùntàn yẹn ò yàtọ̀ sí ọ̀pọ̀ èèyàn tí wọn ò tíì gbọ́ ìhìn rere lónìí. Àwọn olùṣọ́ àgùntàn èké ti pa wọ́n tì, ebi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń pa wọ́n, òùngbẹ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń gbẹ wọ́n, wọn ò sì ní ìrètí kankan pé ọ̀la ń bọ̀ wá dára. Àwa ní ohun tí wọn ò ní: ìyẹn oúnjẹ tẹ̀mí aṣaralóore àti omi atura òtítọ́ tó wà nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. (Aísáyà 55:1, 2) Bá a ṣe ń ronú nípa ipò tẹ̀mí àwọn tó wà láyìíká wa, àánú wọn ń ṣe wá. Bí àánú àwọn èèyàn bá ṣe wá bó ṣe máa ń ṣe Jésù, a ó ṣe gbogbo ohun tó yẹ láti jẹ́ kí wọ́n gbọ́ nípa ohun tí Ìjọba Ọlọ́run máa ṣe.

      19. Báwo la ṣe lè ran akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì wa tó ti kúnjú ìwọ̀n láti di akéde lọ́wọ́ kó lè wù ú láti máa lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ ìwàásù?

      19 Báwo la ṣe lè ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ kí wọ́n lè máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù? Ká sọ pé a fẹ́ gba akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì tó ti yẹ lẹ́ni tó lè bẹ̀rẹ̀ sí í lọ sóde ẹ̀rí níyànjú pé kó bẹ̀rẹ̀ rẹ̀. Tàbí kó jẹ́ pé ńṣe la fẹ́ ran akéde aláìṣiṣẹ́mọ́ kan lọ́wọ́ láti bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìwàásù lẹ́ẹ̀kan sí i. Báwo la ṣe lè ran irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́? A gbọ́dọ̀ wá bí ọ̀rọ̀ wa ṣe máa wọ̀ wọ́n lọ́kàn ni. Rántí pé ohun àkọ́kọ́ tó máa ń ṣẹlẹ̀ sí Jésù ni pé “àánú” àwọn èèyàn máa ń “ṣe é,” á wá bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ wọn. (Máàkù 6:34) Nítorí náà, bá a bá ràn wọ́n lọ́wọ́ débi tí wọ́n á fi máa ní ìyọ́nú fún àwọn ẹlòmíì, àwọn náà á fẹ́ dà bíi Jésù ní ti pé ọkàn wọn á sún wọn láti wàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run fáwọn ẹlòmíì. A lè bi wọ́n pé: “Ọ̀nà wo ni gbígbà tẹ́ ẹ gba ìhìn rere gbọ́ gbà yí ìgbésí ayé yín padà? Àwọn tí ò tíì gbọ́ nípa ìhìn rere yìí ńkọ́, ǹjẹ́ kò yẹ káwọn náà gbọ́? Kí lẹ lè ṣe láti ràn wọ́n lọ́wọ́?” A ò ní gbàgbé ṣá o, pé ìfẹ́ tá a ní fún Jèhófà àti bó ṣe ń wù wá láti jọ́sìn rẹ̀ lolórí ohun tó ń mú ká máa lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ ìwàásù.

      20. (a) Kí ni jíjẹ́ ọmọlẹ́yìn Jésù ń béèrè lọ́wọ́ wa? (b) Kí la máa jíròrò ní orí tó kàn?

      20 Jíjẹ́ ọmọlẹ́yìn Jésù ju kéèyàn kàn máa kọ́ ẹlòmíì ní àwọn ẹ̀kọ́ rẹ̀ tàbí kéèyàn kàn máa fi àwọn ọ̀rọ̀ náà ṣèwà hù lójú ayé lásán. Ó pọn dandan pé káwa náà nírú “ẹ̀mí ìrònú yìí,” tí Jésù ní. (Fílípì 2:5) Nítorí náà, a dúpẹ́ gan-an pé Bíbélì jẹ́ ká mọ èrò Jésù àti bí nǹkan ṣe rí lára rẹ̀ tó fi sọ àwọn ọ̀rọ̀ tó sọ àtàwọn nǹkan tó gbé ṣe! Bá a bá mọ “èrò inú Kristi” lámọ̀dunjú, a óò túbọ̀ mọ ọ̀nà tó tọ́ láti gbà kọ́ bá a ṣe lè máa kíyè sí ohun tó ń ṣe àwọn èèyàn, a ó sì lè máa fi ìyọ́nú hàn sí wọn. Nípa báyìí, a óò lè máa bá àwọn èèyàn lò lọ́nà tí Jésù gbà bá wọn lò. (1 Kọ́ríńtì 2:16) Ní orí tó kàn, a óò jíròrò onírúurú ọ̀nà tí Jésù gbà fi ìfẹ́ hàn sáwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀.

      a Wọ́n ní ọ̀kan lára àwọn ọ̀rọ̀ Gíríìkì tó tíì dáa jù láti fi ṣàpèjúwe ìyọ́nú ni ọ̀rọ̀ Gíríìkì tí wọ́n túmọ̀ sì ‘àánú ṣe é.’ Ìwé kan sọ pé “kì í ṣe pé kéèyàn rí ìyà tó ń jẹ ọmọlàkejì kó sì dunni nìkan ni, ṣùgbọ́n ó ní nínú kéèyàn fẹ́ láti ṣe gbogbo ohun tó bá lè ṣe láti gba onítọ̀hún sílẹ̀ lọ́wọ́ ìnira yẹn tàbí kéèyàn bá a fòpin sí ìyà náà.”

      b Ọ̀rọ̀ àpọ́nlé lédè Gíríìkì tó túmọ̀ sí “ìmọ̀lára fún ọmọnìkejì” ṣeé tú ní olówuuru sí “bá jìyà.”

      Báwo Lo Ṣe Lè Máa Tọ Jésù Lẹ́yìn?

      • Ọ̀nà wo ni Jésù gbà fi ìyọ́nú hàn nínú bó ṣe lo agbára tó wà níkàáwọ́ rẹ̀, báwo la sì ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ rẹ̀?—Mátíù 11:28-30.

      • Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù nínú ọ̀nà tá a gbà ń fi àánú tàbí ìyọ́nú hàn sáwọn ẹlòmíì?—Mátíù 9:9-13; 23:23.

      • Àwọn ìṣe Jésù wo ló fi hàn pé ó mọ bí nǹkan ṣe máa ń rí lára àwọn èèyàn, báwo la sì ṣe lè máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ rẹ̀?—Lúùkù 7:36-50.

      • Ọ̀nà wo ni àpèjúwe aláàánú ará Samáríà gbà fi hàn pé ànímọ́ rere ni ìyọ́nú, báwo la sì ṣe lè fi ẹ̀kọ́ tí àpèjúwe yẹn kọ́ wa sílò?—Lúùkù 10:29-37.

  • “Jésù . . . Nífẹ̀ẹ́ Wọn Dé Òpin”
    “Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”
    • ORÍ KẸRÌNDÍNLÓGÚN

      “Jésù . . . Nífẹ̀ẹ́ Wọn Dé Òpin”

      1, 2. Báwo ni Jésù ṣe lo alẹ́ tó kẹ́yìn pẹ̀lú àwọn àpọ́sítélì rẹ̀, kí sì nìdí tó fi ka wákàtí mélòó kan tó kù yìí sí pàtàkì tó bẹ́ẹ̀?

      BÍ JÉSÙ ṣe kó gbogbo àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ jọ sí yàrá òkè ní Jerúsálẹ́mù, ó mọ̀ pé alẹ́ yẹn lòun máa fi wà pẹ̀lú wọn kẹ́yìn. Àkókò tó máa padà sọ́dọ̀ Bàbá rẹ̀ ti sún mọ́lé. Tó bá fi máa tó wákàtí mélòó kan sí àkókò yẹn, wọ́n máa fi àṣẹ ọba mú un, èyí sì máa jẹ́ ìdánwò ìgbàgbọ́ tí kò rí irú rẹ̀ rí. Síbẹ̀ pẹ̀lú bí ikú rẹ̀ ṣe rọ̀ dẹ̀dẹ̀ tó yẹn, ọkàn rẹ̀ ò kúrò lára àwọn àpọ́sítélì rẹ̀.

      2 Jésù ti sọ fáwọn àpọ́sítélì rẹ̀ pé òun máa tó fi wọ́n sílẹ̀, àmọ́ ní báyìí, ó ṣì ní àwọn nǹkan míì tó fẹ́ bá wọn sọ láti lè fún wọn lókun kí wọ́n bàa lè dúró gbọin lójú àdánwò tí ń bẹ níwájú. Nítorí náà, ńṣe ló lo àkókò ráńpẹ́ tó kù yìí láti kọ́ wọn láwọn ẹ̀kọ́ pàtàkì tó máa jẹ́ kí wọ́n lè dúró bí olùṣòtítọ́. Àwọn ọ̀rọ̀ tó sọ lálẹ́ ọjọ́ yẹn wà lára àwọn ọ̀rọ̀ rẹ̀ tó wọ̀ wọ́n lọ́kàn jù tó sì túbọ̀ mú kí àárín wọn gún régé sí i. Kí nìdí tí ọ̀rọ̀ àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ fi jẹ ẹ́ lógún ju ọ̀rọ̀ ara rẹ̀ lọ? Kí nìdí tó fi ka wákàtí mélòó kan tó kù yìí sí pàtàkì tó bẹ́ẹ̀? Ìfẹ́ ni. Ìfẹ́ tó ní sí wọn jinlẹ̀ gan-an.

      3. Báwo la ṣe mọ̀ pé Jésù ò dúró di alẹ́ ọjọ́ tó lò kẹ́yìn kó tó máa fìfẹ́ hàn sáwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀?

      3 Ọ̀pọ̀ ọdún lẹ́yìn náà nígbà tí àpọ́sítélì Jòhánù ń sọ̀rọ̀, lábẹ́ ìmísí Ọlọ́run nípa ohun tó ṣẹlẹ̀ lálẹ́ ọjọ́ yẹn, ó ní: “Nítorí ó mọ̀ ṣáájú àjọyọ̀ ìrékọjá náà pé wákàtí òun ti dé fún òun láti lọ kúrò ní ayé yìí sọ́dọ̀ Baba, bí Jésù ti nífẹ̀ẹ́ àwọn tirẹ̀ tí wọ́n wà ní ayé, ó nífẹ̀ẹ́ wọn dé òpin.” (Jòhánù 13:1) Kì í ṣe pé Jésù dúró di alẹ́ ọjọ́ yẹn kó tó fi han “àwọn tirẹ̀” pé òun nífẹ̀ẹ́ wọn. Jálẹ̀ gbogbo ìgbà tó fi ṣiṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀, kódà nínú ohun kékeré pàápàá, ó jẹ́ ká rí ẹ̀rí pé òun nífẹ̀ẹ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn òun. Ó bọ́gbọ́n mu nígbà náà pé ká gbé díẹ̀ yẹ̀ wò lára àwọn ọ̀nà tó gbà fi ìfẹ́ hàn, nítorí pé nípa títẹ̀lé àpẹẹrẹ rẹ̀ la fi lè fira wa hàn ní ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ tòótọ́.

      Bó Ṣe Ń Mú Sùúrù

      4, 5. (a) Kí nìdí tí Jésù fi ní láti mú sùúrù fáwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀? (b) Kí ni Jésù ṣe nígbà táwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ mẹ́ta tó mú dání lọ sí ọgbà Gẹtisémánì ò lè máa bá a ṣọ́nà?

      4 Ìfẹ́ àti sùúrù tan mọ́ra. Ìwé 1 Kọ́ríńtì 13:4 sọ pé “Ìfẹ́ a máa ní ìpamọ́ra,” àti pé ìpamọ́ra túmọ̀ sí fífi sùúrù fara dà á fún àwọn ẹlòmíì. Ǹjẹ́ Jésù ní láti mú sùúrù fáwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀? Bẹ́ẹ̀ ni o, ọ̀rọ̀ wọn gba sùúrù! Bá a ṣe rí i ní Orí 3 ìwé yìí, ó pẹ́ káwọn àpọ́sítélì rẹ̀ tó lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀. Àní ó ju ẹ̀ẹ̀kan lọ tí wọ́n ṣe awuyewuye nípa ẹni tó máa jẹ́ ọ̀gá láàárín wọn. Kí ni Jésù ṣe sí i? Ṣó bínú tutọ́ sókè fojú gbà á, bóyá kó bú wọn tàbí kó sọ kòbákùngbé ọ̀rọ̀ sí wọn? Ó tì o. Sùúrù ló tún fi ṣàlàyé fún wọn, kódà nígbà tí “awuyewuye gbígbónájanjan kan” tún dìde lórí ìṣòro yìí kan náà lálẹ́ tó lò kẹ́yìn pẹ̀lú wọn!—Lúùkù 22:24-30; Mátíù 20:20-28; Máàkù 9:33-37.

      5 Nígbà tó ṣe díẹ̀ lálẹ́ ọjọ́ yẹn kan náà, Jésù lọ sí ọgbà Gẹtisémánì tòun ti àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ mọ́kànlá tí wọ́n dúró tì í, ohun kan tó sì dán sùúrù rẹ̀ wò tún ṣẹlẹ̀. Ó ní káwọn mẹ́jọ tó kù dúró, ó sì ní kí Pétérù, Jákọ́bù àti Jòhánù tẹ̀ lé òun lọ sáàárín ọgbà lọ́hùn-ún. Jésù wá sọ fún wọn pé: “Mo ní ẹ̀dùn-ọkàn gidigidi, àní títí dé ikú. Ẹ dúró síhìn-ín, kí ẹ sì máa bá a nìṣó ní ṣíṣọ́nà pẹ̀lú mi.” Ó rìn síwájú díẹ̀, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í gbàdúrà kíkankíkan. Lẹ́yìn àkókò gígùn tó ti ń gbàdúrà, ó padà sọ́dọ̀ àwọn àpọ́sítélì mẹ́ta yìí. Báwo ló ṣe bá wọn? Lákòókò tó ń dójú kọ àdánwò ńlá bẹ́ẹ̀, ǹjẹ́ ẹ jẹ́ mọ̀ pé oorun làwọn wọ̀nyẹn ń sùn ràì! Ǹjẹ́ ó fìbínú sọ̀rọ̀ sí wọn pé wọn ò wà lójúfò? Ó tì o, pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ ló tún fi gbà wọ́n níyànjú. Ohùn jẹ́jẹ́ tó fi bá wọn sọ̀rọ̀ fi hàn pé ó mọ ìnira tó bá wọn àti bó ṣe rẹ̀ wọ́n tó.a Ó ní: “Ní tòótọ́, ẹ̀mí ń háragàgà, ṣùgbọ́n ẹran ara ṣe aláìlera.” Ní gbogbo alẹ́ ọjọ́ yẹn, ńṣe ni Jésù ní sùúrù, kódà lẹ́yìn tó padà lẹ́ẹ̀méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ tó jẹ́ pé ojú oorun yẹn náà ni wọ́n ṣì wà!—Mátíù 26:36-46.

      6. Báwo la ṣe lè ní sùúrù bíi ti Jésù nínú ọ̀nà tá a gbà ń bá àwọn èèyàn lò?

      6 Ẹ̀kọ́ ńlá ló jẹ́ fún wa láti mọ̀ pé Jésù ò ro àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ pin. Sùúrù tó ní ò já sásán torí pé àwọn ọkùnrin olóòótọ́ yìí wá mọ̀ lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn bó ṣe ṣe pàtàkì tó láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni tó wà lójúfò. (1 Pétérù 3:8; 4:7) Báwo la ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù nínú bá a ṣe ń ṣe sáwọn ẹlòmíì? A ní láti máa mú sùúrù, pàápàá jù lọ, àwọn alàgbà. Ó lè jẹ́ pé ìgbà tí ìṣòro ka alàgbà kan láyà tàbí tí àníyàn kan ti gbà á lọ́kàn làwọn Kristẹni kan á tún gbé ìṣòro tiwọn lọ bá a. Ìgbà míì sì wà táwọn tó nílò ìrànlọ́wọ́ ò tiẹ̀ ní fẹ́ gba ìmọ̀ràn bọ̀rọ̀. Bó ṣe wù kó rí, ńṣe làwọn alàgbà tó bá ní sùúrù máa ń fúnni ní ìtọ́ni “pẹ̀lú ìwà tútù” wọn a sì máa “fi ọwọ́ pẹ̀lẹ́tù mú agbo.” (2 Tímótì 2:24, 25; Ìṣe 20:28, 29) Ó yẹ káwọn òbí náà máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù nípa jíjẹ́ onísùúrù torí pé àwọn ìgbà míì lè wà táwọn ọmọ ò ní tètè gba ìbáwí. Ìfẹ́ àti sùúrù ló máa ran àwọn òbí lọ́wọ́ tí wọn ò fi ní jẹ́ kó sú wọn láti máa kọ́ àwọn ọmọ wọn lẹ́kọ̀ọ́. Kékeré kọ́ lèrè òbí tó bá ṣe sùúrù fáwọn ọmọ rẹ̀.—Sáàmù 127:3.

      Bó Ṣe Ń Bójú Tó Wọn

      7. Àwọn ọ̀nà wo ni Jésù gbà ṣe ohun táwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ nílò fún wọn?

      7 Ẹni tó bá nífẹ̀ẹ́ kì í jẹ́ kí ọ̀ràn tiẹ̀ nìkan gbà á lọ́kàn. (1 Jòhánù 3:17, 18) Ìfẹ́ “kì í wá àwọn ire tirẹ̀ nìkan.” (1 Kọ́ríńtì 13:5) Ìfẹ́ ló mú kí Jésù ṣe ohun táwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ nílò fún wọn. Ọ̀pọ̀ ìgbà ló máa ń ṣe ohun tí wọ́n nílò kí wọ́n tiẹ̀ tó sọ ọ́. Nígbà tó kíyè sí i pé ó ti rẹ̀ wọ́n, ó ní kí wọ́n tẹ̀ lé òun ní àwọn “nìkan sí ibi tí ó dá,” kí wọ́n “sì sinmi díẹ̀.” (Máàkù 6:31) Nígbà tó sì róye pé ebi ti ń pa wọ́n, ẹnì kan ò sọ fún un kó tó bọ́ wọn, pẹ̀lú ẹgbẹẹgbẹ̀rún èèyàn tó wá láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.—Mátíù 14:19, 20; 15:35-37.

      8, 9. (a) Kí ló jẹ́ ká mọ̀ pé Jésù mọ ohun táwọn ọmọ ẹ̀yìn nílò nípa tẹ̀mí àti pé ó ṣe é fún wọn? (b) Nígbà tí Jésù wà lórí òpó igi oró, báwo ló ṣe jẹ́ ká mọ̀ pé ọ̀rọ̀ àbójútó ìyá òun jẹ òun lógún?

      8 Jésù mọ ohun táwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ nílò láti lè túbọ̀ sún mọ́ Ọlọ́run, ó sì ṣeé fún wọn. (Mátíù 4:4; 5:3) Ó sábà máa ń fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ní àfiyèsí àrà ọ̀tọ̀ nígbà tó bá ń kọ́ gbogbo èèyàn lẹ́kọ̀ọ́. Ká kúkú sọ pé torí àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ ló ṣe ṣe Ìwàásù Lórí Òkè. (Mátíù 5:1, 2, 13-16) Nígbà tó bá fi àpèjúwe kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́, “ní ìdákọ́ńkọ́, yóò ṣàlàyé ohun gbogbo fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀.” (Máàkù 4:34) Jésù yan “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” láti lè rí i pé ebi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ò pa àwọn ọmọlẹ́yìn òun lẹ́yìn tóun bá ti padà sí ọ̀run. Ẹgbẹ́ ẹrú yìí, tó jẹ́ kìkì àwọn ẹni àmì òróró arákùnrin Jésù lórí ilẹ̀ ayé kò tíì yéé fi ìṣòtítọ́ fúnni ní oúnjẹ tẹ̀mí “ní àkókò tí ó bẹ́tọ̀ọ́ mu” láti ọ̀rúndún kìíní Sànmánì Kristẹni títí dòní olónìí.—Mátíù 24:45.

      9 Lọ́jọ́ tí Jésù máa kú, ó jẹ́ ká rí i lọ́nà tó ṣeni láàánú pé ipò tẹ̀mí àwọn tí òun fẹ́ràn jẹ òun lógún gan-an. Fojú inú wo ohun tó ṣẹlẹ̀. Jésù wà lórí òpó igi níbi tó ti ń jẹ̀rora burúkú burúkú. Kó tó lè mí sínú, ó ti ní láti kọ́kọ́ fi ẹsẹ̀ ti ara rẹ̀ sókè. Kò sì síyè méjì pé ìrora ńlá gbáà nìyẹn á jẹ́ fún un bí ara rẹ̀ ṣe ń fà ya níbi ojú ìṣó tí wọ́n fi kàn án lẹ́sẹ̀ tí ẹ̀yìn rẹ̀ tí wọ́n ti fi ẹgba bà jẹ́ sì ń ha òpó náà. Kó tó lè sọ̀rọ̀, ó ní láti mí sínú, èyí sì ti ní láti fa ìnira àti ìrora fún un gan-an ni. Síbẹ̀ náà, pẹ̀lú bí àtisọ̀rọ̀ ṣe nira fún Jésù tó yìí, kó tó gbẹ́mìí mì, ó kúkú tiraka sọ̀rọ̀ kan tó fi hàn pé ó nífẹ̀ẹ́ Màríà ìyá rẹ̀ púpọ̀. Nígbà tó rí Màríà ìyá rẹ̀ àti àpọ́sítélì Jòhánù tí wọ́n dúró sítòsí rẹ̀, ó gbóhùn sókè débi táwọn tó dúró nítòsí fi lè gbọ́, ó sọ fún ìyá rẹ̀ pé: “Obìnrin, wò ó! Ọmọkùnrin rẹ!” Ó sì sọ fún Jòhánù pé: “Wò ó! Ìyá rẹ!” (Jòhánù 19:26, 27) Jésù mọ̀ pé yàtọ̀ sí pé àpọ́sítélì náà tó jẹ́ olóòótọ́ á ṣe ohun tó máa dín ẹ̀dùn ọkàn Màríà kù, ó tún máa pèsè nípa tara àti nípa tẹ̀mí fún un.b

      Àwọn àwòrán tó wà ní ojú ìwé 164, 165

      Àwọn òbí tí wọ́n bá mọṣẹ́ wọn níṣẹ́ á máa ní sùúrù, wọ́n á sì máa bójú tó àwọn ọmọ wọn

      10. Báwo làwọn òbí ṣe lè ṣe bíi ti Jésù nínú bíbójú tó àwọn ọmọ wọn?

      10 Àwọn òbí tí wọ́n bá mọ ojúṣe wọn á rí i pé ó yẹ kéèyàn máa ṣàṣàrò lórí àpẹẹrẹ tí Jésù fi lélẹ̀. Bàbá tó fẹ́ràn ìdílé rẹ̀ á máa ṣe ohun tí ìdílé rẹ̀ ń fẹ́ fún wọn. (1 Tímótì 5:8) Olórí ìdílé tó mọ ohun tó tọ́ á rí i pé òun àti ìdílé òun ń ní àkókò ìsinmi àti eré ìnàjú lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan. Ní pàtàkì jù lọ, àwọn òbí tó jẹ́ Kristẹni ní láti rí i pé àwọn ọmọ wọn ò rẹ̀yìn nínú ìjọsìn Ọlọ́run. Lọ́nà wo? Irú àwọn òbí bẹ́ẹ̀ máa ń ṣètò fún ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé, wọ́n á máa ṣe é déédéé, wọ́n á sì máa rí i pé ìkẹ́kọ̀ọ́ náà ń dùn mọ́ àwọn ọmọ tó sì ń fún wọn níṣìírí. (Diutarónómì 6:6, 7) Nínú ọ̀rọ̀ àti nínú àpẹẹrẹ táwọn òbí ń fi lélẹ̀, wọ́n ní láti máa jẹ́ káwọn ọmọ wọn mọ̀ pé iṣẹ́ ìwàásù ṣe pàtàkì púpọ̀ àti pé mímúra sílẹ̀ ká tó lọ sípàdé àti wíwà ní gbogbo ìpàdé jẹ́ ara ìjọsìn tí a ò gbọ́dọ̀ pa jẹ.—Hébérù 10:24, 25.

      Bó Ṣe Máa Ń Wù Ú Láti Dárí Jini

      11. Kí ni Jésù kọ́ àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ nípa ìdáríjì?

      11 Dídáríjini wà lára ọ̀nà tá a lè gbà fi ìfẹ́ hàn. (Kólósè 3:13, 14) Ìwé 1 Kọ́ríńtì 13:5 sọ pé ìfẹ́ “kì í kọ àkọsílẹ̀ ìṣeniléṣe.” Lọ́pọ̀ ìgbà, Jésù jẹ́ káwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ mọ bí ìdáríjì ṣe ṣe pàtàkì tó. Ó rọ̀ wọ́n pé kí wọ́n máa dárí ji àwọn ẹlòmíì “kì í ṣe, Títí dé ìgbà méje, bí kò ṣe, Títí dé ìgbà àádọ́rin lé méje.” (Mátíù 18:21, 22) Ó kọ́ wọn pé kí wọ́n darí ji ẹlẹ́ṣẹ̀ kan lẹ́yìn tí wọ́n bá ti fún un ní ìbáwí tó sì ronú pìwà dà. (Lúùkù 17:3, 4) Jésù máa ń fi àpẹẹrẹ tiẹ̀ kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́ ni, ìyẹn ló fi yàtọ̀ sáwọn alágàbàgebè Farisí tó jẹ́ pé wọn kì í ṣe ohun tí wọ́n bá sọ. (Mátíù 23:2-4) Ẹ jẹ́ ká wá wo bí Jésù ṣe fi hàn pé tinútinú lòun fi ń dárí ji àwọn èèyàn nígbà tí ẹnì kan tó fọkàn tán já a kulẹ̀.

      Àwòrán Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 166

      12, 13. (a) Lọ́nà wo ni Pétérù gbà padà lẹ́yìn Jésù lálẹ́ ọjọ́ tí wọ́n mú Un? (b) Báwo ni ohun tí Jésù ṣe lẹ́yìn tó jíǹde ṣe fi hàn pé kó fọ̀rọ̀ mọ sórí kó kàn máa wàásù ìdáríjì?

      12 Jésù àti àpọ́sítélì Pétérù sún mọ́ ara wọn dáadáa. Ọlọ́yàyà èèyàn ni Pétérù, àmọ́ nígbà míì kì í fara balẹ̀. Jésù mọrírì àwọn ànímọ́ rere tí Pétérù ní, ó sì gbé àwọn iṣẹ́ pàtàkì lé e lọ́wọ́. Pétérù pẹ̀lú Jákọ́bù àti Jòhánù fójú ara wọn rí àwọn iṣẹ́ ìyanu kan táwọn àpọ́sítélì mẹ́sàn-án yòókù ò rí. (Mátíù 17:1, 2; Lúùkù 8:49-55) Bá a ṣe sọ lẹ́ẹ̀kan, Pétérù wà lára àwọn àpọ́sítélì tí Jésù mú lọ sínú ọgbà Gẹtisémánì lóru ọjọ́ tí wọ́n mú Un. Síbẹ̀ lóru ọjọ́ yẹn kan náà, lẹ́yìn tí Júdásì fi Jésù hàn tí wọ́n sì lọ fi sí àhámọ́, Pétérù àtàwọn àpọ́sítélì tó kù pa Jésù tì, wọ́n sì sá lọ. Lẹ́yìn náà, Pétérù ṣe ọkàn akin, ó dúró níta ibi tí wọ́n ti ń fèrú gbẹ́jọ́ Jésù. Síbẹ̀, ìbẹ̀rù mú Pétérù, ó sì ṣe àṣìṣe kan tó burú jáì, ó parọ́ lẹ́ẹ̀mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ pé òun ò mọ Jésù rí! (Mátíù 26:69-75) Kí ni Jésù ṣe? Ká ní ìwọ ni ọ̀rẹ́ tó o fọkàn tán ṣe ohun tó dùn ọ́ tó báyìí sí, kí lò bá ṣe?

      13 Jésù ti múra tán láti darí ji Pétérù. Ó mọ̀ pé ẹ̀rí ọkàn Pétérù ti ń nà án ní pàṣán torí ẹ̀ṣẹ̀ tó dá yẹn. Ó ṣe tán, àpọ́sítélì yẹn kábàámọ̀ ohun tó ṣe “ó sì bara jẹ́, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí sunkún.” (Máàkù 14:72) Lọ́jọ́ tí Jésù jíǹde, ó fara han Pétérù, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé torí kó lè tù ú nínú, kó sì jẹ́ kó mọ̀ pé òun ṣì gbọ́kàn lé e ló ṣe fara hàn án. (Lúùkù 24:34; 1 Kọ́ríńtì 15:5) Kò pé oṣù méjì lẹ́yìn náà tí Jésù fi pọ́n Pétérù lé nípa jíjẹ́ kó mú ipò iwájú láti jẹ́rìí fún ogunlọ́gọ̀ tó wà ní Jerúsálẹ́mù lọ́jọ́ Pẹ́ńtíkọ́sì. (Ìṣe 2:14-40) Ká má sì gbàgbé pé Jésù ò tìtorí pé àwọn àpọ́sítélì pa á tì kó wá di gbogbo wọn sínú o. Dípò ìyẹn, lẹ́yìn tó jíǹde, ó ṣì pè wọ́n ní “arákùnrin mi.” (Mátíù 28:10) Ǹjẹ́ kó ṣe kedere pé Jésù ò fi mọ sórí kó máa kọ́ni láti dárí jini, òun fúnra rẹ̀ dárí ji àwọn tó ṣẹ̀ ẹ́?

      14. Kí nìdí tá a fi gbọ́dọ̀ fi kọ́ra láti máa darí ji ẹni tó bá ṣẹ̀ wá, báwo la sì ṣe lè fi hàn pé a fẹ́ láti darí ji ẹni tó bá ṣẹ̀ wá tọkàntọkàn?

      14 Gẹ́gẹ́ bí ọmọ ẹ̀yìn Kristi, a gbọ́dọ̀ kọ́ bá a ṣe lè máa darí ji àwọn ẹlòmíì. Kí nìdí? Bí Jésù ṣe jẹ́ ẹni pípé, kò sẹ́ni pípé nínú àwa àtàwọn tó lè ṣẹ̀ wá. Lóòrèkóòrè là máa ń kọsẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ tàbí nínú ìṣe. (Róòmù 3:23; Jákọ́bù 3:2) Nígbà tó bá yẹ ká dárí ji ẹni tó ṣẹ̀ wá, ó tọ́ ká ṣe bẹ́ẹ̀ kí Ọlọ́run bàa lè dárí ji àwa náà. (Máàkù 11:25) Báwo la ṣe lè máa darí ji àwọn tó bá ṣẹ̀ wá tọkàntọkàn? Ọ̀pọ̀ ìgbà ló jẹ́ pé ìfẹ́ máa jẹ́ ká lè gbójú fo ẹ̀ṣẹ̀ pẹ́ẹ́pẹ̀ẹ̀pẹ́ àti kùdìẹ̀ kudiẹ àwọn ẹlòmíì. (1 Pétérù 4:8) Nígbà táwọn tó ṣẹ̀ wá bá ronú pìwà dà tọkàntọkàn bíi ti Pétérù, ó dájú pé àwa náà máa fẹ́ darí ji ẹni náà tọkàntọkàn bíi ti Jésù. Dípò tí a ó fi dì wọ́n sínú, ohun tó dáa ni pé ká jẹ́ kó tán nínú wa, ká sì gbàgbé ẹ̀. (Éfésù 4:32) Bá a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, ńṣe là ń mú kí àlàáfíà rídìí jókòó nínú ìjọ, bákan náà, àwa fúnra wa á ní àlàáfíà àti ìbàlẹ̀ ọkàn.—1 Pétérù 3:11.

      Bó Ṣe Fi Hàn Pé Òun Gbọ́kàn Lé Wọn

      15. Kí nìdí tí Jésù fi gbọ́kàn lé àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ láìfi ti àwọn kùdìẹ̀ kudiẹ wọn ṣe?

      15 Ìfẹ́ àti ìgbọ́kànlé jọ ń rìn pọ̀ ni. Ìfẹ́ “á máa gba ohun gbogbo gbọ́.”c (1 Kọ́ríńtì 13:7) Ìfẹ́ ló sún Jésù láti fi hàn pé tinútinú lòun fi gbọ́kàn lé àwọn ọmọlẹ́yìn òun láìfi ti àìpé wọn ṣe. Ó gbọ́kàn lé wọn ó sì gbà gbọ́ pé wọ́n nífẹ̀ẹ́ Jèhófà dénú àti pé wọ́n fẹ́ ṣe ìfẹ́ Rẹ̀. Kódà láwọn ìgbà tí wọ́n bá ṣe àṣìṣe, Jésù kì í fura òdì sí wọn, kó wá máa wádìí ohun tó mú wọn ṣe é. Bí àpẹẹrẹ, nígbà tí àpọ́sítélì Jákọ́bù àti Jòhánù lọ sọ fún ìyá wọn pé kí Jésù jẹ́ káwọn jókòó sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ nínú Ìjọba rẹ̀, Jésù ò tìtorí ìyẹn bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiyè méjì nípa ìdúróṣinṣin wọn tàbí kó yọ wọ́n kúrò lára àwọn àpọ́sítélì.—Mátíù 20:20-28.

      16, 17. Àwọn iṣẹ́ wo ni Jésù gbé lé àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ lọ́wọ́?

      16 Káwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ bàa lè mọ̀ pé ó gbọ́kàn lé wọn, ó yan onírúuru iṣẹ́ fún wọn. Lẹ́ẹ̀méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ tó fi iṣẹ́ ìyanu pèsè oúnjẹ tó sì bọ́ ogunlọ́gọ̀, àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ló yàn láti pín oúnjẹ náà. (Mátíù 14:19; 15:36) Nígbà tó ń múra sílẹ̀ fún Ìrékọjá tó ṣe kẹ́yìn, ó rán Pétérù àti Jòhánù pé kí wọ́n lọ sí Jerúsálẹ́mù kí wọ́n sì mú kí gbogbo nǹkan wà ní sẹpẹ́. Àwọn ló rí sí bí wọ́n ṣe rí ọ̀dọ́ àgùntàn, wáìnì, àkàrà aláìwú, ewébẹ̀ kíkorò àtàwọn nǹkan míì tí wọ́n lò. Iṣẹ́ yìí kì í ṣe iṣẹ́ yẹpẹrẹ rárá, torí ohun pàtàkì ni Ìrékọjá jẹ́ nínú Òfin Mósè, Jésù sì gbọ́dọ̀ rí i pé gbogbo ohun tí Òfin náà là kalẹ̀ lòun tẹ̀ lé. Yàtọ̀ síyẹn, lálẹ́ ọjọ́ yẹn tí Jésù fi Ìrántí Ikú rẹ̀ lọ́lẹ̀, wáìnì àti àkàrà aláìwú yìí kan náà ni Jésù lò gẹ́gẹ́ bí ohun ìṣàpẹẹrẹ.—Mátíù 26:17-19; Lúùkù 22:8, 13.

      17 Jésù rí i pé ó bójú mu láti gbé iṣẹ́ tó tiẹ̀ tún ṣe pàtàkì gan-an lé àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ lọ́wọ́. Bá a ṣe sọ lẹ́ẹ̀kan, àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ tó jẹ́ ẹni àmì òróró tó yàn lórí ilẹ̀ ayé ló gbé iṣẹ́ lé lọ́wọ́ láti máa fi oúnjẹ tẹ̀mí bọ́ àwọn tó máa di ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀. (Lúùkù 12:42-44) Wàá sì tún rántí pé ìkáwọ́ àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ ló fi iṣẹ́ wíwàásù àti sísọni di ọmọ ẹ̀yìn tó jẹ́ iṣẹ́ bàǹtà banta sí. (Mátíù 28:18-20) Kódà nísinsìnyí tó ti wà lọ́run tó sì ti ń ṣàkóso, abẹ́ àbójútó àwọn ọkùnrin tó rí pé wọ́n tóótun, ìyẹn “àwọn ẹ̀bùn tí ó jẹ́ ènìyàn” ló fi ìjọ àwọn èèyàn rẹ̀ tó wà láyé sí.—Éfésù 4:8, 11, 12.

      18-20. (a) Báwo la ṣe lè fi hàn pé a ní ìgbọ́kànlé nínú àwọn tá a jọ jẹ́ onígbàgbọ́? (b) Báwo la ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù nínú bó ṣe máa ń fa iṣẹ́ lé àwọn ẹlòmíì lọ́wọ́? (d) Kí la máa jíròrò ní orí tó kàn?

      18 Báwo la ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù nínú ọ̀nà tá a gbà ń bá àwọn ẹlòmíì lò? Bá a bá ń fi hàn pé a nígbàgbọ́ nínú àwọn tá a jọ jẹ́ onígbàgbọ́ tá a sì fọkàn tán wọn, ńṣe là ń fi bá a ṣe nífẹ̀ẹ́ wọn tó hàn. Ẹ jẹ́ ká máa rántí pé ohun tó dáa nípa àwọn èèyàn ni ìfẹ́ máa ń rí kì í rí ohun tó burú nípa wọn. Báwọn ẹlòmíì bá ṣe ohun tó dùn wá, èyí táá máa ṣẹlẹ̀ lóòrèkóòrè, ìfẹ́ ò ní jẹ́ ká tètè rò pé wọ́n dìídì ṣe é ni. (Mátíù 7:1, 2) Bó bá jẹ́ pé ibi táwọn tá a jọ jẹ́ onígbàgbọ́ dáa sí là ń wò, ńṣe la óò máa gbé wọn ró dípò tá a ó fi máa fẹnu ya wọ́n lulẹ̀.—1 Tẹsalóníkà 5:11.

      19 Ṣé àwa náà lè máa fa iṣẹ́ lé àwọn míì lọ́wọ́ bíi ti Jésù? Ohun tó dáa jù fáwọn tí wọ́n wà nípò àṣẹ nínú ìjọ ni pé kí wọ́n máa fa àwọn iṣẹ́ tó bójú mu tó sì nítumọ̀ lé àwọn ará lọ́wọ́, kí wọ́n ní ìgbọ́kànlé nínú wọn, pé wọ́n á sa gbogbo ipá wọn. Nípa bẹ́ẹ̀, àwọn alàgbà tó ti pẹ́ nínú òtítọ́ á lè dá àwọn ọ̀dọ́kùnrin tó tóótun tí wọ́n “ń nàgà” láti ṣèrànwọ́ nínú ìjọ lẹ́kọ̀ọ́ nípa ohun tó yẹ kí wọ́n mọ̀ tó sì máa wúlò fún wọn. (1 Tímótì 3:1; 2 Tímótì 2:2) Irú ìdálẹ́kọ̀ọ́ bẹ́ẹ̀ ṣe kókó. Bí Jèhófà ṣe ń mú kí àwọn tó ń wọlé wá sínú ètò rẹ̀ máa pọ̀ sí i, bẹ́ẹ̀ náà ló máa pọn dandan pé ká máa dá àwọn ọkùnrin tó tóótun lẹ́kọ̀ọ́ kí wọ́n lè máa bójú tó àwọn tó ṣẹ̀ṣẹ̀ ń dé.—Aísáyà 60:22.

      20 Àpẹẹrẹ àtàtà ni Jésù fi lélẹ̀ fún wa nípa bó ṣe yẹ ká nífẹ̀ẹ́ àwọn ẹlòmíì. Nínú gbogbo ọ̀nà tó yẹ ká máa gbà tẹ̀ lé e, títẹ̀lé àpẹẹrẹ ìfẹ́ tó fi lélẹ̀ ló ṣe pàtàkì jù. Ní orí tó kàn, a óò jíròrò nípa bó ṣe fìfẹ́ hàn sí wa lọ́nà kan tó ṣàrà ọ̀tọ̀, ìyẹn bó ṣe fínnúfíndọ̀ fi ẹ̀mí rẹ̀ lélẹ̀ nítorí wa.

      a Àárẹ̀ ara nìkan kọ́ ló fa oorun táwọn àpọ́sítélì Jésù ń sùn. Àkọsílẹ̀ ìṣẹ̀lẹ̀ kan náà yẹn tó wà ní Lúùkù 22:45 sọ pé Jésù “bá wọn tí wọ́n ń tòògbé nítorí ẹ̀dùn-ọkàn.”

      b Ó hàn gbangba pé opó ni Màríà nígbà yẹn àti pé àwọn ọmọ rẹ̀ yòókù ò tíì di ọmọ ẹ̀yìn Jésù.—Jòhánù 7:5.

      c Èyí ò túmọ̀ sí pé ìfẹ́ gọ̀ o, pé ẹní bá nífẹ̀ẹ́ dùn-ún tàn jẹ. Ohun tó túmọ̀ sí ni pé ìfẹ́ kì í tọ pinpin láìnídìí, kì í sì í fura òdì. Ìfẹ́ kì í tètè torí ohun tó ṣẹlẹ̀ ka àwọn èèyàn sẹ́ni burúkú láìkọ́kọ́ mọ ohun tó fà á.

      Báwo Lo Ṣe Lè Máa Tọ Jésù Lẹ́yìn?

      • Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká gba ìmọ̀ràn tí Jésù fún wa nípa dídáríjì àwọn ẹlòmíì?—Mátíù 6:14, 15.

      • Báwo la ṣe lè fi ẹ̀kọ́ tó wà nínú àkàwé tí Jésù ṣe yìí sílò nípa ìdí tá a fi gbọ́dọ̀ máa ní ẹ̀mí ìdáríjì?—Mátíù 18:23-35.

      • Báwo ni Jésù ṣe gba tàwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ rò, ọ̀nà wo la sì lè gbà fìwà jọ ọ́?—Mátíù 20:17-19; Jòhánù 16:12.

      • Báwo ni Jésù ṣe jẹ́ kí Pétérù mọ̀ pé Òun ṣì ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ̀, ọ̀nà wo làwa náà sì lè gbà jẹ́ káwọn ẹlòmíì mọ̀ pé a gbọ́kàn lé wọn?—Lúùkù 22:31, 32.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́