-
Ìtùnú Fáwọn Tó Ń JìyàIlé Ìṣọ́—2003 | January 1
-
-
Ọlọ́run kò dá èèyàn láti jìyà. Dípò ìyẹn, ó fi èrò inú àti ara pípé jíǹkí tọkọtaya ẹ̀dá ènìyàn àkọ́kọ́, ìyẹn Ádámù àti Éfà, ó ṣètò ọgbà dáradára kan tí wọ́n á máa gbé, ó sì yan iṣẹ́ alárinrin tó ń máyọ̀ wá fún wọn. (Jẹ́nẹ́sísì 1:27, 28, 31; 2:8) Àmọ́ ṣá o, tí wọn ò bá fẹ́ ki ayọ̀ wọn bà jẹ́, wọ́n ní láti tẹ́wọ́ gba ìṣàkóso Ọlọ́run, kí wọ́n sì gbà pé òun ló lẹ́tọ̀ọ́ láti pinnu ohun tí ó tọ́ àti èyí tí kò tọ́. Àṣẹ Ọlọ́run yẹn ni igi kan tí a pè ní “igi ìmọ̀ rere àti búburú” dúró fún. (Jẹ́nẹ́sísì 2:17) Ádámù àti Éfà yóò fi hàn pé àwọn fi ara wọn sábẹ́ Ọlọ́run bí wọ́n bá pa àṣẹ rẹ̀ tó sọ pé wọn ò gbọ́dọ̀ jẹ lára èso igi náà mọ́.a
-
-
Ìtùnú Fáwọn Tó Ń JìyàIlé Ìṣọ́—2003 | January 1
-
-
a Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé tá a ṣe lórí Jẹ́nẹ́sísì 2:17 nínú The Jerusalem Bible sọ pé “ìmọ̀ rere àti búburú” jẹ́ “agbára láti pinnu . . . ohun tó jẹ́ rere àti ohun tó jẹ́ ibi, kéèyàn sì ṣe èyí tí ó tọ́, ó jẹ́ níní òmìnira pátápátá, èyí tó mú kí ènìyàn gbàgbéra pé ẹnì kan ló dá a.” Ó fi kún un pé: “Ẹ̀ṣẹ̀ àkọ́kọ́ jẹ́ gbígbéjàko ipò Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ọba aláṣẹ.”
-