-
Jèhófà Ni “Olùṣí Àwọn Àṣírí Payá”Ilé Ìṣọ́—2012 | June 15
-
-
4. Àwọn wo ló para pọ̀ di irú ọmọ obìnrin náà, kí sì ni irú ọmọ yìí máa ṣe?
4 Láìpẹ́ lẹ́yìn ìṣọ̀tẹ̀ tó wáyé ní ọgbà Édẹ́nì, Jèhófà ṣèlérí pé “obìnrin” kan máa bí “irú ọmọ” kan.a (Ka Jẹ́nẹ́sísì 3:15.) Ní àsẹ̀yìnwá-àsẹ̀yìnbọ̀, irú ọmọ yìí máa pa ejò náà, Sátánì, ní orí. Nígbà tó yá, Jèhófà ṣí i payá pé irú ọmọ náà máa wá láti ìlà ìdílé Ábúráhámù, láti orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì, pé ó máa jẹ́ ẹ̀yà Júdà àti pé ó máa jẹ́ àtọmọdọ́mọ Dáfídì Ọba. (Jẹ́n. 22:15-18; 49:10; Sm. 89:3, 4; Lúùkù 1:30-33) Kristi Jésù ni apá àkọ́kọ́ lára irú ọmọ náà. (Gál. 3:16) Àwọn ẹni àmì òróró tó wà nínú ìjọ Kristẹni ni apá kejì lára irú ọmọ náà. (Gál. 3:26-29) Jésù àti àwọn ẹni àmì òróró yìí ló para pọ̀ di Ìjọba Ọlọ́run, Ìjọba yìí sì ni Ọlọ́run máa lò láti fọ́ Sátánì túútúú.—Lúùkù 12:32; Róòmù 16:20.
5, 6. (a) Agbára ńlá mélòó ni Dáníẹ́lì àti Jòhánù sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀? (b) Kí ni àwọn orí ẹranko ẹhànnà tí ìwé Ìṣípayá sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ dúró fún?
5 Àsọtẹ́lẹ̀ àkọ́kọ́ tí Ọlọ́run sọ nínú ọgbà Édẹ́nì yẹn tún fi hàn pé Sátánì náà máa ní “irú ọmọ” tirẹ̀. Irú ọmọ Sátánì yìí máa bá irú ọmọ obìnrin náà ṣọ̀tá. Àwọn wo ló para pọ̀ di irú ọmọ ejò náà? Gbogbo àwọn tó kórìíra Ọlọ́run tí wọ́n sì ń ta ko àwọn èèyàn rẹ̀ bíi ti Sátánì ni. Ọjọ́ pẹ́ tí Sátánì ti ń ṣètò irú ọmọ rẹ̀ sí onírúurú ẹgbẹ́ òṣèlú, tàbí àwọn ìjọba. (Lúùkù 4:5, 6) Àmọ́, díẹ̀ lára àwọn ìjọba èèyàn ló tíì ní ipa tó lágbára gan-an lórí àwọn èèyàn Ọlọ́run, ì báà jẹ́ orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì àtijọ́ tàbí ìjọ àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró. Kí nìdí tí kókó yìí fi ṣe pàtàkì? Ìdí ni pé ó jẹ́ ká mọ ìdí tó fi jẹ́ pé mẹ́jọ péré lára irú àwọn ìjọba alágbára bẹ́ẹ̀ ni Dáníẹ́lì àti Jòhánù rí nínú ìran.
-
-
Jèhófà Ni “Olùṣí Àwọn Àṣírí Payá”Ilé Ìṣọ́—2012 | June 15
-
-
7. Kí ni àkọ́kọ́ lára orí ẹranko náà dúró fún, kí sì nìdí?
7 Àkọ́kọ́ lára orí ẹranko náà dúró fún orílẹ̀-èdè Íjíbítì. Kí nìdí? Ìdí ni pé Íjíbítì ni agbára ayé tó kọ́kọ́ mú àwọn èèyàn Ọlọ́run ní ọ̀tá. Àwọn àtọmọdọ́mọ Ábúráhámù, ẹni tí Ọlọ́run ṣèlérí pé ipasẹ̀ rẹ̀ ni irú ọmọ obìnrin náà máa gbà wá, di púpọ̀ rẹpẹtẹ ní ilẹ̀ Íjíbítì. Lẹ́yìn náà, àwọn ará Íjíbítì wá ń pọ́n àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lójú. Sátánì gbìyànjú láti pa àwọn èèyàn Ọlọ́run rẹ́ kí irú ọmọ náà tó dé. Lọ́nà wo? Ó mú kí Fáráò pa gbogbo ọmọ ọkùnrin tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì bí. Jèhófà mú kí ìsapá yìí forí ṣánpọ́n, ó sì dá àwọn èèyàn rẹ̀ sílẹ̀ lóko ẹrú àwọn ará Íjíbítì. (Ẹ́kís. 1:15-20; 14:13) Ẹ̀yìn náà ló wá fìdí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kalẹ̀ sí Ilẹ̀ Ìlérí.
8. Kí ni èkejì lára orí ẹranko náà dúró fún, kí ló sì gbìyànjú láti ṣe?
8 Èkejì lára orí ẹranko náà dúró fún orílẹ̀-èdè Ásíríà. Ìjọba alágbára yìí náà gbìyànjú láti pa àwọn èèyàn Ọlọ́run rẹ́. Òótọ́ ni pé Jèhófà lo orílẹ̀-èdè Ásíríà láti fìyà jẹ ìjọba ẹ̀yà mẹ́wàá Ísírẹ́lì nítorí wọ́n di abọ̀rìṣà àti ọlọ̀tẹ̀. Àmọ́, orílẹ̀-èdè Ásíríà tún wá gbéjà ko Jerúsálẹ́mù. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ńṣe ni Sátánì ń wá bó ṣe máa pa ìlà ìdílé ọba tí Jésù máa gbà wá run. Ìgbéjàkò yìí kò sí lára ohun tí Jèhófà ní lọ́kàn láti ṣe, ó sì dá àwọn èèyàn rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ olóòótọ́ sílẹ̀ lọ́nà ìyanu nípa pípa àwọn ọ̀tá náà run.—2 Ọba 19:32-35; Aísá. 10:5, 6, 12-15.
-
-
Jèhófà Ni “Olùṣí Àwọn Àṣírí Payá”Ilé Ìṣọ́—2012 | June 15
-
-
13 Jèhófà lo Ilẹ̀ Ọba Mídíà òun Páṣíà láti mú àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ ṣẹ nígbà tó gba ìjọba lọ́wọ́ Bábílónì tó sì dá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pa dà sí ìlú ìbílẹ̀ wọn. (2 Kíró. 36:22, 23) Àmọ́, agbára ayé kan náà yìí tún fẹ́rẹ̀ẹ́ pa àwọn èèyàn Ọlọ́run rẹ́. Ìwé Ẹ́sítérì nínú Bíbélì sọ nípa ìdìtẹ̀ kan tó wáyé. Ọkùnrin kan báyìí tórúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Hámánì tó jẹ́ igbá kejì ọba Páṣíà ló sì dìtẹ̀ náà. Ó ṣètò pé kí wọ́n pa gbogbo àwọn Júù tó ń gbé ní Ilẹ̀ Ọba Páṣíà gbígbòòrò run, ó sì dá ọjọ́ kan pàtó tí ìpẹ̀yàrun náà máa wáyé. Ọpẹ́lọpẹ́ bí Jèhófà ṣe dá sí ọ̀rọ̀ náà ló yọ àwọn èèyàn rẹ̀, tó sì tún gbà wọ́n lọ́wọ́ irú ọmọ Sátánì tó ń ṣe kèéta sí wọn. (Ẹ́sít. 1:1-3; 3:8, 9; 8:3, 9-14) Ó bá a mu wẹ́kú bí Ìwé Mímọ́ ṣe fi ìkẹrin lára orí ẹranko inú ìwé Ìṣípayá ṣàpẹẹrẹ Mídíà òun Páṣíà.
-
-
Jèhófà Ni “Olùṣí Àwọn Àṣírí Payá”Ilé Ìṣọ́—2012 | June 15
-
-
16. Kí ni Áńtíókọ́sì Kẹrin ṣe?
16 Lẹ́yìn tí ilẹ̀ Gíríìsì ti ṣẹ́gun Páṣíà, ó ṣàkóso lórí ilẹ̀ àwọn èèyàn Ọlọ́run. Ní àkókò yìí àwọn Júù ti pa dà sí Ilẹ̀ Ìlérí, wọ́n sì ti tún tẹ́ńpìlì tó wà ní Jerúsálẹ́mù kọ́. Àyànfẹ́ Ọlọ́run ni wọ́n ṣì jẹ́, tẹ́ńpìlì tí wọ́n tún kọ́ náà sì ni ojúkò ìjọsìn tòótọ́. Àmọ́ ní ọ̀rúndún kejì ṣáájú Sànmánì Kristẹni (Ṣ.S.K.), ilẹ̀ Gíríìsì tó jẹ́ ìkarùn-ún lára orí ẹranko ẹhànnà náà, gbéjà ko àwọn èèyàn Ọlọ́run. Áńtíókọ́sì Kẹrin tó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn tó gba ilẹ̀ ọba Alẹkisáńdà tí wọ́n pín, gbé ojúbọ òrìṣà sórí ilẹ̀ tẹ́ńpìlì tó wà ní Jerúsálẹ́mù, ó sì ṣòfin pé pípa ni wọ́n máa pa ẹnikẹ́ni tí wọ́n bá rí tó ń ṣe ẹ̀sìn àwọn Júù. Ẹ ò rí i pé ìkórìíra ńlá gbáà lèyí jẹ́ látọ̀dọ̀ irú ọmọ Sátánì! Àmọ́ kò pẹ́ lẹ́yìn náà tí wọ́n fi gba agbára ayé lọ́wọ́ ilẹ̀ Gíríìsì. Kí ni ìkẹfà lára orí ẹranko ẹhànnà yìí dúró fún?
-
-
Jèhófà Ni “Olùṣí Àwọn Àṣírí Payá”Ilé Ìṣọ́—2012 | June 15
-
-
17. Ipa pàtàkì wo ni ìkẹfà lára orí ẹranko náà kó nínú ìmúṣẹ Jẹ́nẹ́sísì 3:15?
17 Róòmù ló ń ṣàkóso lọ́wọ́ nígbà tí Jòhánù rí ìran ẹranko ẹhànnà náà. (Ìṣí. 17:10) Róòmù tó jẹ́ ìkẹfà lára orí ẹranko yìí kó ipa pàtàkì nínú ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ tó wà nínú Jẹ́nẹ́sísì 3:15. Sátánì lo àwọn aláṣẹ ìlú Róòmù láti ṣe irú ọmọ obìnrin náà lọ́ṣẹ́ fúngbà díẹ̀, èyí tó já sí pé ó pa á “ní gìgísẹ̀.” Lọ́nà wo? Wọ́n gbẹ́jọ́ Jésù lórí àwọn ẹ̀sùn èké tí wọ́n fi kàn án pé ó dìtẹ̀ sí ìjọba, wọ́n sì dájọ́ ikú fún un. (Mát. 27:26) Àmọ́ kò pẹ́ tí ọgbẹ́ náà fi jinná torí pé Jèhófà jí Jésù dìde.
18. (a) Orílẹ̀-èdè tuntun wo ni Jèhófà yàn, kí sì nìdí? (b) Ọ̀nà wo ni irú ọmọ ejò náà ń gbà bá a nìṣó láti máa ṣe kèéta sí irú ọmọ obìnrin náà?
18 Àwọn aṣáájú ẹ̀sìn ní orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì lẹ̀dí àpò pọ̀ pẹ̀lú àwọn ará Róòmù lòdì sí Jésù, èyí tó pọ̀ jù lára àwọn èèyàn orílẹ̀-èdè náà ló sì kọ Jésù sílẹ̀. Ìdí nìyẹn tí Jèhófà fi pa Ísírẹ́lì nípa tara tí wọ́n jẹ́ èèyàn rẹ̀ tì. (Mát. 23:38; Ìṣe 2:22, 23) Ó wá yan orílẹ̀-èdè tuntun ìyẹn ni “Ísírẹ́lì Ọlọ́run.” (Gál. 3:26-29; 6:16) Ìjọ àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró ni orílẹ̀-èdè náà, àwọn Júù àti àwọn Kèfèrí ló sì wà nínú rẹ̀. (Éfé. 2:11-18) Lẹ́yìn tí Jésù ti kú tó sì ti jíǹde, irú ọmọ ejò náà ń bá a nìṣó láti máa ṣe kèéta sí irú ọmọ obìnrin náà. Ó ju ìgbà kan lọ tí Róòmù gbìyànjú láti pa ìjọ Kristẹni tó jẹ́ apá kejì lára irú ọmọ náà rẹ́.c
-
-
Jèhófà Ni “Olùṣí Àwọn Àṣírí Payá”Ilé Ìṣọ́—2012 | June 15
-
-
a Obìnrin yìí dúró fún ètò Jèhófà tó dà bí ìyàwó, àwọn áńgẹ́lì tó wà lókè ọ̀run ló sì para pọ̀ di ètò Ọlọ́run yìí.—Aísá. 54:1; Gál. 4:26; Ìṣí. 12:1, 2.
-
-
Jèhófà Ni “Olùṣí Àwọn Àṣírí Payá”Ilé Ìṣọ́—2012 | June 15
-
-
c Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Róòmù pa ìlú Jerúsálẹ́mù run lọ́dún 70 Sànmánì Kristẹni, ìgbéjàkò yìí kò sí lára ìmúṣẹ Jẹ́nẹ́sísì 3:15. Ní àkókò yẹn, Ísírẹ́lì nípa tara kì í ṣe orílẹ̀-èdè àyànfẹ́ Ọlọ́run mọ́.
-