-
Ẹ Máa Wo Ọ̀dọ̀ Jèhófà Fún ÌtùnúIlé-Ìṣọ́nà—1996 | November 1
-
-
5 Lọ́nà yìí, tọkọtaya ẹlẹ́ṣẹ̀ náà bẹ̀rẹ̀ sí í kú. Nígbà tí ó ń dájọ́ ikú, Ọlọ́run tún sọ fún Ádámù pé: “A fi ilẹ̀ bú nítorí rẹ; ní ìpọ́njú ni ìwọ óò máa jẹ nínú rẹ̀ ní ọjọ́ ayé rẹ gbogbo; ẹ̀gún òun òṣùṣú ni yóò máa hù jáde fún ọ, ìwọ óò sì máa jẹ ewéko ìgbẹ́.” (Jẹ́nẹ́sísì 3:17, 18) Nípa báyìí, Ádámù àti Éfà pàdánù ìfojúsọ́nà ti sísọ ilẹ̀ ayé tí a kò tí ì ro di párádísè kan. Níwọ̀n bí a ti lé wọn kúrò ní Édẹ́nì, wọ́n gbọ́dọ̀ lo agbára wọn láti rí oúnjẹ tí a ń làágùn kí a tó rí, láti inú ilẹ̀ tí a ti fi bú. Àwọn àtọmọdọ́mọ wọn, níwọ̀n bí wọ́n ti jogún ipò kíkú, ẹlẹ́ṣẹ̀ yìí, wọ́n wá bẹ̀rẹ̀ sí í nílò ìtùnú gidigidi.—Róòmù 5:12.
-
-
Ẹ Máa Wo Ọ̀dọ̀ Jèhófà Fún ÌtùnúIlé-Ìṣọ́nà—1996 | November 1
-
-
8 Jèhófà pète láti fi ìkún omi kárí ayé pa ayé búburú yẹn run, ṣùgbọ́n lákọ̀ọ́kọ́, ó mú kí Nóà kan ọkọ̀ láti gba ẹ̀mí là. Nípa báyìí, a gba ìran ènìyàn àti ọ̀wọ́ àwọn ẹranko là. Ẹ wo bí ara yóò ti tu Nóà àti ìdílé rẹ̀ tó lẹ́yìn Ìkún Omi náà bí wọ́n ti ń jáde kúrò nínú ọkọ̀ sínú ilẹ̀ ayé tí a fọ̀ mọ́ tónítóní! Ẹ wo bí yóò ti tù wọ́n nínú tó pé a ti mú ègún tí ń bẹ lórí ilẹ̀ kúrò, ní mímú kí ìgbòkègbodò iṣẹ́ àgbẹ̀ rọrùn gidigidi! Ní tòótọ́, àsọtẹ́lẹ̀ Lámékì já sóòótọ́, Nóà sì gbé ní ìbámu pẹ̀lú ìtumọ̀ orúkọ rẹ̀. (Jẹ́nẹ́sísì 8:21) Gẹ́gẹ́ bí olùṣòtítọ́ ìránṣẹ́ Ọlọ́run, Nóà jẹ́ irinṣẹ́ ní mímú “ìtùnú” wá fún aráyé títí dé ìwọ̀n àyè kan. Bí ó ti wù kí ó rí, agbára ìdarí búburú ti Sátánì àti àwọn áńgẹ́lì ẹ̀mí èṣù rẹ̀ kò dópin pẹ̀lú Ìkún Omi náà, aráyé sì ń bá a nìṣó láti máa kérora lábẹ́ ẹrù ìnira ti ẹ̀ṣẹ̀, àìsàn, àti ikú.
-