-
“Ẹ Jẹ́ Kí Ìfaradà Ṣe Iṣẹ́ Rẹ̀ Pé Pérépéré”Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016 | April
-
-
12. Kí la rí kọ́ lára àwọn kérúbù tí Jèhófà ní kó máa ṣọ́ ọgbà Édẹ́nì?
12 Áńgẹ́lì onípò-ńlá làwọn kérúbù. Lẹ́yìn tí Ádámù àti Éfà dẹ́ṣẹ̀, Jèhófà rán àwọn kan lára àwọn kérúbù náà wá sórí ilẹ̀ ayé. Iṣẹ́ tó ní kí wọ́n wá ṣe yàtọ̀ pátápátá sí èyí tí wọ́n ń ṣe lọ́run. Àpẹẹrẹ wọn kọ́ wa pé a lè fara dà á tí ètò Ọlọ́run bá gbé iṣẹ́ kan tó dà bíi pé ó le fún wa. Bíbélì sọ pé Jèhófà “yan àwọn kérúbù sí ìlà-oòrùn ọgbà Édẹ́nì àti abẹ idà tí ń jó lala, tí ń yí ara rẹ̀ láìdáwọ́ dúró láti máa ṣọ́ ọ̀nà tí ó lọ síbi igi ìyè náà.”[2] (Wo àfikún àlàyé.) (Jẹ́nẹ́sísì 3:24) Bíbélì ò sọ pé àwọn kérúbù náà ráhùn tàbí kí wọ́n rò pé àwọn ti ga ju ẹni tó ń ṣe irú iṣẹ́ bẹ́ẹ̀ lọ. Wọn ò jẹ́ kó sú wọn, wọn ò sì yarí pé àwọn ò lè ṣe iṣẹ́ náà mọ́. Kàkà bẹ́ẹ̀, wọ́n dúró síbi tí Jèhófà ní kí wọ́n wà títí tí wọ́n fi parí iṣẹ́ náà, ó sì ṣeé ṣe kó jẹ́ pé nígbà Ìkún-omi tó wáyé ní ohun tó lé ní ẹgbẹ̀rún kan ó lé ọgọ́rùn-ún mẹ́fà [1,600] ọdún lẹ́yìn náà ni wọ́n tó pa dà sọ́run!
-
-
“Ẹ Jẹ́ Kí Ìfaradà Ṣe Iṣẹ́ Rẹ̀ Pé Pérépéré”Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016 | April
-
-
^ [2] (ìpínrọ̀ 12) Bíbélì ò sọ iye àwọn kérúbù tí Jèhófà gbé iṣẹ́ yìí fún.
-