-
Rírú Ẹbọ Tí Jèhófà Yóò Tẹ́wọ́ GbàIlé Ìṣọ́—1999 | February 1
-
-
Nígbà tó yá, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ nígbà tí wọ́n ti di géńdé, Kéènì àti Ébẹ́lì rúbọ sí Jèhófà. Nígbà tó jẹ́ pé olùṣọ́ àgùntàn ni Ébẹ́lì, kò yani lẹ́nu pé “àwọn àkọ́bí nínú agbo ẹran rẹ̀ . . . , àní àwọn apá tí ó lọ́ràá nínú wọn” ló mú wá. Ní òdìkejì ẹ̀wẹ̀, “àwọn èso kan tí ilẹ̀ mú jáde” ni Kéènì fi rúbọ. Jèhófà tẹ́wọ́ gba ẹbọ Ébẹ́lì, ṣùgbọ́n “òun kò fi ojú rere kankan wo Kéènì àti ọrẹ ẹbọ rẹ̀.” (Jẹ́nẹ́sísì 4:3-5) Èé ṣe?
Àwọn kan sọ pé ohun tó fà á ni pé ẹbọ Ébẹ́lì wá láti inú “àwọn àkọ́bí nínú agbo ẹran rẹ̀,” àmọ́ ti Kéènì jẹ́ “àwọn èso kan tí ilẹ̀ mú jáde.” Ṣùgbọ́n, ọ̀ràn náà kì í ṣe bóyá ohun tí Kéènì fi rúbọ dára tàbí kò dára, nítorí àkọsílẹ̀ náà sọ pé Jèhófà fi ojú rere “wo Ébẹ́lì àti ọrẹ ẹbọ rẹ̀,” kò sì fi ojú rere kankan “wo Kéènì àti ọrẹ ẹbọ rẹ̀.” Nítorí náà, bí ọkàn-àyà olùjọsìn náà ti rí ni Jèhófà wò. Ní ṣíṣe bẹ́ẹ̀, kí ló rí? Hébérù 11:4 sọ pé “nípa ìgbàgbọ́” ni Ébẹ́lì rú ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà, ó hàn gbangba pé, Kéènì kò ní ìgbàgbọ́ tó mú kí a tẹ́wọ́ gba ẹbọ Ébẹ́lì.
Ní ti èyí, ó yẹ fún àfiyèsí pé ọrẹ ẹbọ Ébẹ́lì ní títa ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nínú. Ó ti lè parí èrò sí pé, ìlérí Ọlọ́run nípa irú-ọmọ tí a óò pa ní gìgísẹ̀ yóò ní fífi nǹkan ẹlẹ́mìí rúbọ nínú. Ọrẹ ẹbọ Ébẹ́lì nígbà náà ti lè jẹ́ ẹ̀bẹ̀ fún ètùtù, ó sì fi ìgbàgbọ́ hàn pé Ọlọ́run yóò pèsè ẹbọ ìpẹ̀tù fún ẹ̀ṣẹ̀ nígbà tó bá tó àkókò.
-
-
Rírú Ẹbọ Tí Jèhófà Yóò Tẹ́wọ́ GbàIlé Ìṣọ́—1999 | February 1
-
-
Bíbélì kò sọ bí Jèhófà ṣe fi hàn pé òun tẹ́wọ́ gba ẹbọ Ébẹ́lì. Àwọn kan sọ pé iná bọ́ sí i láti ọ̀run, ó sì jó o. Ọ̀nà yòówù kó jẹ́, gbàrà tí Kéènì ti mọ̀ pé a kò tẹ́wọ́ gba ẹbọ òun, “ìbínú Kéènì . . . gbóná gidigidi, ojú rẹ̀ sì bẹ̀rẹ̀ sí rẹ̀wẹ̀sì.” (Jẹ́nẹ́sísì 4:5) Ìjàngbọ̀n mà ni Kéènì ń fà lẹ́sẹ̀ yìí.
-