-
“Ẹ Di Aláfarawé Ọlọ́run”Ilé Ìṣọ́—2008 | October 1
-
-
Ọ̀rọ̀ Ọlọrun gba àwọn Kristẹni tòótọ́ níyànjú pé: “Nítorí náà, ẹ di aláfarawé Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí í ṣe olùfẹ́ ọ̀wọ́n.” (Éfésù 5:1) Àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyẹn fi hàn pé Ọlọ́run ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú àwọn tó ń sìn ín. Lọ́nà wo? Jèhófà Ọlọ́run dá èèyàn ní àwòrán ara rẹ̀. (Jẹ́nẹ́sísì 1:26, 27) Ọlọ́run tipa bẹ́ẹ̀ dá àwọn ànímọ́ bíi tirẹ̀ mọ́ àwa èèyàn.a Nítorí náà, nígbà tí Bíbélì rọ àwọn Kristẹni pé kí wọ́n “di aláfarawé Ọlọ́run,” ńṣe ló dà bíi pé Jèhófà fúnra rẹ̀ ń sọ fún wọn pé: ‘Mo gba ẹ̀rí yín jẹ́. Mo mọ̀ lóòótọ́ pé aláìpé ni yín, àmọ́ ẹ ṣì lè fìwà jọ mí dé àyè kan.’
-
-
“Ẹ Di Aláfarawé Ọlọ́run”Ilé Ìṣọ́—2008 | October 1
-
-
a Ìwé Kólósè 3:9, 10 jẹ́ ká mọ̀ pé dídá tá a dá wa ní àwòrán Ọlọ́run ní í ṣe pẹ̀lú àwọn ìwà àbínibí. Bíbélì rọ àwọn tó fẹ́ múnú Ọlọ́run dùn pé kí wọ́n máa fi “àkópọ̀ ìwà tuntun” ṣèwà hù, èyí tó máa sọ wọ́n “di tuntun . . . ní ìbámu pẹ̀lú àwòrán [Ọlọ́run] tí ó dá” wọn.
-