-
A ó Máa Rìn Ní Orúkọ Jèhófà Ọlọ́run WaIlé Ìṣọ́—2005 | September 1
-
-
A ó Máa Rìn Ní Orúkọ Jèhófà Ọlọ́run Wa
“Àwa, ní tiwa, yóò máa rìn ní orúkọ Jèhófà Ọlọ́run wa fún àkókò tí ó lọ kánrin, àní títí láé.”—MÍKÀ 4:5.
1. Báwo ni ìwà àwọn èèyàn ṣe rí nígbà ayé Nóà, báwo ni Nóà sì ṣe yàtọ̀ sáwọn tó kù?
ÉNỌ́KÙ lẹni àkọ́kọ́ tí Bíbélì sọ pé ó bá Ọlọ́run rìn. Nóà sì ni ẹnì kejì. Àkọsílẹ̀ náà sọ fún wa pé: “Nóà jẹ́ olódodo. Ó fi ara rẹ̀ hàn ní aláìní-àléébù láàárín àwọn alájọgbáyé rẹ̀. Nóà bá Ọlọ́run tòótọ́ rìn.” (Jẹ́nẹ́sísì 6:9) Gbogbo èèyàn ti yapa kúrò nínú ìjọsìn mímọ́ nígbà ayé Nóà. Ohun tó túbọ̀ wá mú kí nǹkan burú sí i lákòókò yẹn ni àwọn áńgẹ́lì aláìṣòótọ́ tí wọ́n ṣe ohun tí kò bójú mu rárá ní ti pé wọ́n wá fẹ́ àwọn ọmọbìnrin èèyàn. Wọ́n bí àwọn ọmọ tá a pè ní Néfílímù, “àwọn ni alágbára ńlá” tàbí “àwọn ọkùnrin olókìkí,” láyé ìgbàanì. Abájọ tí ìwà ipá fi kún orí ilẹ̀ ayé! (Jẹ́nẹ́sísì 6:2, 4, 11) Síbẹ̀, Nóà fi hàn pé òun jẹ́ aláìlẹ́bi àti “oníwàásù òdodo.” (2 Pétérù 2:5) Nígbà tí Ọlọ́run pàṣẹ fún Nóà pé kó kan ọkọ̀ áàkì láti fi gba ẹ̀mí là, ó ṣègbọràn ó sì “bẹ̀rẹ̀ sí ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Ọlọ́run ti pa láṣẹ fún un. Ó ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́.” (Jẹ́nẹ́sísì 6:22) Láìsí àní-àní, Nóà bá Ọlọ́run rìn.
2, 3. Àpẹẹrẹ àtàtà wo ni Nóà fi lélẹ̀ fún wa lónìí?
2 Nóà wà lára àwọn ẹlẹ́rìí olóòótọ́ tí Pọ́ọ̀lù to orúkọ wọn lẹ́sẹẹsẹ nígbà tó kọ̀wé pé: “Nípa ìgbàgbọ́ ni Nóà, lẹ́yìn fífún un ní ìkìlọ̀ àtọ̀runwá nípa àwọn ohun tí a kò tíì rí, fi ìbẹ̀rù Ọlọ́run hàn, ó sì kan ọkọ̀ áàkì fún ìgbàlà agbo ilé rẹ̀; àti nípasẹ̀ ìgbàgbọ́ yìí, ó dá ayé lẹ́bi, ó sì di ajogún òdodo tí ó wà ní ìbámu pẹ̀lú ìgbàgbọ́.” (Hébérù 11:7) Àpẹẹrẹ títayọ gbáà lèyí mà jẹ́ o! Ó dá Nóà lójú gan-an pé ọ̀rọ̀ Jèhófà yóò ṣẹ, débi pé ó lo ọ̀pọ̀ àkókò, okun àti ohun ìní rẹ̀ láti fi ṣe ohun tí Ọlọ́run pa láṣẹ. Bákan náà lónìí, ọ̀pọ̀ ló kọ àwọn àǹfààní ńlá tí ì bá jẹ́ tiwọn nínú ayé sílẹ̀, tí wọ́n ń lo àkókò wọn, agbára wọn àti ohun ìní wọn láti ṣe ohun tí Jèhófà pa láṣẹ. Ìgbàgbọ́ irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ jọni lójú gan-an, yóò sì yọrí sí ìgbàlà wọn àti tàwọn ẹlòmíràn.—Lúùkù 16:9; 1 Tímótì 4:16.
3 Kò rọrùn rárá fún Nóà àti ìdílé rẹ̀ láti fi ìgbàgbọ́ tí wọ́n ní ṣèwà hù bí kò ṣe rọrùn fún Énọ́kù tó jẹ́ baba ńlá Nóà, bá a ṣe jíròrò rẹ̀ nínú àpilẹ̀kọ tó ṣáájú. Bó ṣe rí nígbà ayé Énọ́kù náà ló rí nígbà ayé Nóà, àwọn olùjọsìn tòótọ́ kéré níye gan-an, ẹni mẹ́jọ péré ló jẹ́ olóòótọ́ tí wọ́n sì la Ìkún Omi náà já. Nóà wàásù òdodo nínú ayé tó kún fún ìwà ipá àti ìṣekúṣe. Yàtọ̀ síyẹn, òun àti ìdílé rẹ̀ tún kan ọkọ̀ áàkì onígi kan tó rí gìrìwò. Wọ́n múra sílẹ̀ de ìkún omi kan tó máa kárí ayé, bó tilẹ̀ jẹ́ pé kò sẹ́ni tó rí irú ìkún omi bẹ́ẹ̀ rí ṣáájú àkókò yẹn. Ìyẹn ti ní láti jẹ́ nǹkan àjèjì lójú àwọn tó ń wò wọ́n.
4. Kí ni Jésù sọ pé àwọn tó gbé ayé lákòókò kan náà pẹ̀lú Nóà kùnà láti ṣe?
4 Ohun kan tó yẹ ká kíyè sí ni pé, nígbà tí Jésù ń sọ̀rọ̀ nípa ọjọ́ Nóà, kò sọ̀rọ̀ nípa ìwà ipá, ìsìn èké, tàbí ìṣekúṣe, bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn nǹkan wọ̀nyí náà burú jáì. Ohun tí Jésù dá àwọn èèyàn náà lẹ́bi fún ni pé wọ́n kọ̀ láti kọbi ara sí ìkìlọ̀ tí wọ́n gbọ́. Ó sọ pé wọ́n “ń jẹ, wọ́n sì ń mu, àwọn ọkùnrin ń gbéyàwó, a sì ń fi àwọn obìnrin fúnni nínú ìgbéyàwó, títí di ọjọ́ tí Nóà wọ ọkọ̀ áàkì.” Kí ló burú nínú kéèyàn máa jẹ, kó máa mu, kó gbéyàwó, kó sì fa ìyàwó fúnni? Lójú tiwọn, ohun tó yẹ kéèyàn ṣe láyé ni wọ́n ń ṣe yẹn! Àmọ́, ìkún omi ń bọ̀, Nóà sì ń wàásù òdodo. Ó yẹ kí ọ̀rọ̀ tó ń sọ àti ìwà rẹ̀ ti jẹ́ ìkìlọ̀ fún wọn. Síbẹ̀, wọn “kò . . . fiyè sí i títí ìkún omi fi dé, tí ó sì gbá gbogbo wọn lọ.”—Mátíù 24:38, 39.
5. Àwọn ànímọ́ wo ni Nóà àti ìdílé rẹ̀ nílò?
5 Tá a bá fojú inú wo bí nǹkan ṣe rí lákòókò yẹn, a óò rí ọgbọ́n tó wà nínú ọ̀nà tí Nóà gbà gbé ìgbésí ayé rẹ̀. Àmọ́ ṣá o, láwọn ọjọ́ tó ṣáájú ìkún omi yẹn, ó gba ìgboyà gan-an kéèyàn tó lè máa ṣe ohun tó yàtọ̀ sóhun tí gbogbo èèyàn yòókù ń ṣe. Ó gba ìgbàgbọ́ tó lágbára gan-an kí Nóà àti ìdílé rẹ̀ tó lè kan ọkọ̀ áàkì gìrìwò náà kí wọ́n sì kó onírúurú ẹranko sínú rẹ̀. Ǹjẹ́ àwọn kan lára àwọn kéréje tó jẹ́ olóòótọ́ èèyàn yẹn tiẹ̀ fìgbà kan sọ pé ó wu àwọn káwọn má ṣe dá yàtọ̀, káwọn sì máa gbé irú ìgbésí ayé táwọn èèyàn yòókù ń gbé? Kódà, bí irú èrò bẹ́ẹ̀ bá tiẹ̀ ṣèèṣì wá sí wọn lọ́kàn, wọn ò jẹ́ kí ìgbàgbọ́ wọn yẹ̀. Ẹ̀yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ni ìgbàgbọ́ Nóà tó yọrí sí ìgbàlà fún un nígbà tí Ìkún Omi náà dé, ìyẹn sì ju iye ọdún tí èyíkéyìí lára wa ní láti fara da ètò nǹkan ìsinsìnyí. Àmọ́, Jèhófà mú ìdájọ́ ṣẹ sórí gbogbo àwọn tó ń gbé ìgbésí ayé tó dára lójú ara wọn yẹn tí wọn ò sì fiyè sí nǹkan tó ń ṣẹlẹ̀ lákòókò tí wọ́n ń gbé náà.
-
-
A ó Máa Rìn Ní Orúkọ Jèhófà Ọlọ́run WaIlé Ìṣọ́—2005 | September 1
-
-
À Ń Kọbi Ara Sáwọn Ìkìlọ̀ Jèhófà
9. Báwo ni ayé òde òní ṣe jọ ayé tó wà ṣáájú Ìkún Omi?
9 Nígbà ayé Nóà, Jèhófà pa àwọn èèyàn run torí ìwà ipá bíburú jáì táwọn olubi èèyàn àtàwọn Néfílímù ń hù. Òde òní wá ńkọ́? Ǹjẹ́ ìwà ipá inú ayé ìsinsìnyí dín kù sí tìgbà ayé Nóà? Rárá o! Láfikún sí i, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọjọ́ Nóà ti rí, bẹ́ẹ̀ náà làwọn èèyàn òde òní ṣe ń bá iṣẹ́ wọn ojoojúmọ́ lọ, tí wọ́n ń gbé ìgbésí ayé wọn lọ́nà tó tọ́ lójú ara wọn, tí wọn kò sì kọbi ara sí ìkìlọ̀ tí wọ́n ń gbọ́. (Lúùkù 17:26, 27) Ǹjẹ́ ó tiẹ̀ yẹ ká ṣiyèméjì pé Jèhófà yóò tún pa àwọn ẹni ibi run? Ó tì o.
10. (a) Ìkìlọ̀ wo ni àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì ń sọ ní àsọtúnsọ? (b) Kí lohun tó bọ́gbọ́n mu jù lọ láti ṣe lónìí?
10 Ọgọ́rọ̀ọ̀rún ọdún ṣáájú Ìkún Omi ni Énọ́kù ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìparun tó máa ṣẹlẹ̀ ní àkókò tiwa yìí. (Júúdà 14, 15) Jésù náà sọ̀rọ̀ nípa “ìpọ́njú ńlá” tó ń bọ̀. (Mátíù 24:21) Àwọn wòlíì mìíràn náà sì tún kìlọ̀ nípa àkókò yẹn. (Ìsíkíẹ́lì 38:18-23; Dáníẹ́lì 12:1; Jóẹ́lì 2:31, 32) Bákan náà la tún kà á nínú ìwé Ìṣípayá nípa bí ìparun ìkẹyìn yẹn ṣe máa ṣẹlẹ̀ gan-an. (Ìṣípayá 19:11-21) Àwa lẹ́nì kọ̀ọ̀kan ń fara wé Nóà, a sì ń sa gbogbo ipá wa gẹ́gẹ́ bí oníwàásù òdodo. À ń kọbi ara sáwọn ìkìlọ̀ Jèhófà, a sì ń fìfẹ́ ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ láti ṣe bákan náà. Fún ìdí yìí, à ń bá Ọlọ́run rìn bí Nóà ṣe bá a rìn. Láìsí àní-àní, ó ṣe pàtàkì pé kí ẹnikẹ́ni tó bá fẹ́ wà láàyè máa bá Ọlọ́run rìn nìṣó. Báwo la óò ṣe ṣèyẹn lójú gbogbo wàhálà tá à ń dojú kọ lójoojúmọ́? A ní láti ní ìgbàgbọ́ tó lágbára pé ohun tí Ọlọ́run ní lọ́kàn láti ṣe yóò ṣẹ.—Hébérù 11:6.
-