-
Ṣé Ayé àti Ọ̀run Ní Ìbẹ̀rẹ̀?Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
3. Kí ló mú káwa èèyàn yàtọ̀ sáwọn ẹranko?
Lẹ́yìn tí Jèhófà dá ayé, ó dá àwọn ohun abẹ̀mí sínú ẹ̀. Àwọn ewéko àtàwọn ẹranko ló kọ́kọ́ dá. Lẹ́yìn náà, “Ọlọ́run sì dá èèyàn ní àwòrán rẹ̀.” (Ka Jẹ́nẹ́sísì 1:27.) Kí ló mú káwa èèyàn ṣàrà ọ̀tọ̀ nínú gbogbo nǹkan tí Ọlọ́run dá? Ohun tó mú ká ṣàrà ọ̀tọ̀ ni pé àwòrán Ọlọ́run ni wá, torí náà a lè ní àwọn ìwà àti ìṣe tí Ọlọ́run ní, irú bí ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo. Ó tún dá wa lọ́nà tá a fi lè kọ́ àwọn èdè tuntun, a lè mọyì àwọn ohun tó rẹwà, a sì lè gbádùn orin lóríṣiríṣi. Ohun míì tá a tún lè ṣe àmọ́ táwọn ẹranko ò lè ṣe ni pé a lè jọ́sìn Ẹlẹ́dàá wa.
-
-
Ṣé Ayé àti Ọ̀run Ní Ìbẹ̀rẹ̀?Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
5. Ó bọ́gbọ́n mu láti gbà pé òótọ́ ni ohun tí Bíbélì sọ nípa bí ayé àti ọ̀run ṣe bẹ̀rẹ̀
Nínú Jẹ́nẹ́sísì orí kìíní, Bíbélì sọ bí ayé àtàwọn nǹkan tó wà nínú ẹ̀ ṣe bẹ̀rẹ̀. Ṣó o gbà pé òótọ́ ni ohun tí Bíbélì sọ, àbí ìtàn àròsọ lásán ni? Wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà, kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:
Ṣé ohun tí Bíbélì sọ ni pé ọjọ́ mẹ́fà oníwákàtí-mẹ́rìnlélógún (24) ni Ọlọ́run fi dá ayé àtàwọn ohun tó wà nínú ẹ̀?
Ṣé o rò pé ohun tí Bíbélì sọ nípa bí ayé àti ọ̀run ṣe bẹ̀rẹ̀ bọ́gbọ́n mu? Kí nìdí tó o fi sọ bẹ́ẹ̀?
Ka Jẹ́nẹ́sísì 1:1, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:
Àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì sọ pé ayé àti ọ̀run ní ìbẹ̀rẹ̀. Báwo ni ohun tí wọ́n sọ yìí ṣe bá ohun tó o ṣẹ̀ṣẹ̀ kà tán nínú Bíbélì yẹn mu?
Èrò àwọn kan ni pé ńṣe ni Ọlọ́run jẹ́ kí àwọn ohun kéékèèké kan bẹ̀rẹ̀ sí í yíra pa dà, tí wọ́n sì di oríṣiríṣi àwọn ohun alààyè. Ka Jẹ́nẹ́sísì 1:21, 25, 27, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:
Ṣé ohun tí Bíbélì sọ ni pé ńṣe ni Ọlọ́run kọ́kọ́ ṣe àwọn ohun kéékèèké kan táwọn nǹkan náà wá ń yíra pa dà di ẹja, oríṣiríṣi ẹranko, àtàwa èèyàn? Àbí ńṣe ló dá ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní “irú tiwọn”?b
-