-
Ẹyẹ Ìwò—Kí Ló Mú Un Yàtọ̀?Jí!—1997 | January 8
-
-
Àwọn ẹyẹ ìwò máa ń fò lọ́nà àgbàyanu. Ìran wọn dùn-ún wò bí wọ́n ti ń lọ sókè láìlo ìyẹ́ ní ṣíṣe ìyípo fífẹ̀, tí wọ́n ń fojú wá oúnjẹ ní àgbègbè tí ó wà nísàlẹ̀. Lọ́nà rírọrùn, wọ́n máa ń dárà lófuurufú—títàkìtì àti fífò nídoríkodò fún ìgbà díẹ̀—ní pàtàkì, nígbà eré ìfẹ́sọ́nà àti, nígbà míràn, ó lè jọ pé wọ́n ń ṣe é fún ìdárayá lásán. Bernd Heinrich ṣàpèjúwe bí ẹyẹ ìwò ṣe ń fò dáradára nínú ìwé Ravens in Winter pé: “Ó ń rà bàbà, ó sì ń yí bìrìpó bí ẹdùn ààrá dúdú kan tí ń já bọ́ láti òfuurufú, tàbí ó máa ń yára fò ṣòòròṣò láìlu apá.” Ó fi kún un pé ó jẹ́ “àfiṣàpẹẹrẹ ìṣẹ̀dá pípé nínú afẹ́fẹ́, ó sì tún ní agbára ìṣe púpọ̀ sí i.” A ti gbọ́ pé agbára tí ẹyẹ ìwò ní láti fò ni ìdí tí Nóà fi yàn án bí ẹ̀dá tí a kọ́kọ́ rán jáde láti inú ọkọ̀ áàkì nígbà Ìkún Omi náà.—Jẹ́nẹ́sísì 8:6, 7.
-
-
Ẹyẹ Ìwò—Kí Ló Mú Un Yàtọ̀?Jí!—1997 | January 8
-
-
Nínú Bíbélì, ẹyẹ ìwò ní ìtayọlọ́lá ti pé òun ni ẹyẹ tí a kọ́kọ́ dárúkọ ní pàtó.—Jẹ́nẹ́sísì 8:7.
-