-
Majẹmu Ọlọrun Pẹlu “Ọ̀rẹ́” Rẹ̀ Ti Ṣanfaani fun Araadọta Ọkẹ NisinsinyiÀìléwu Kárí-Ayé Labẹ “Ọmọ-Aládé Alaafia”
-
-
3, 4. (a) Ki ni ó ṣakawe idiwọn giga ti Jehofa gbekari igbagbọ ati igbẹkẹle ti Abrahamu ní ninu rẹ̀? (b) Pẹlu awọn ọ̀rọ̀ wo ni Jehofa fi mu itolẹsẹẹsẹ ọ̀rọ̀ rẹ̀ ninu Isaiah 41:8 wá sí otente giga nla?
3 Ọkunrin onigbagbọ ati agbegbeesẹ yẹn wá lati ilu Uri ti awọn ará Kaldea, oun si ni ẹni ti a kọkọ pè ní Heberu. (Genesisi 14:13) Idanimọ yii ni a wá lò fun awọn atọmọdọmọ rẹ̀ ti orilẹ-ede Israeli. (Filippi 3:5) Ní oju iwoye sisọ Abrahamu di ọ̀rẹ́ rẹ̀, Jehofa Ọlọrun tun mú un wọ inu diẹ ninu awọn ọran aṣiri Rẹ̀. Eyi ni ohun ti a kọ sinu Genesisi 18:17-19 sì fihan.
-
-
Majẹmu Ọlọrun Pẹlu “Ọ̀rẹ́” Rẹ̀ Ti Ṣanfaani fun Araadọta Ọkẹ NisinsinyiÀìléwu Kárí-Ayé Labẹ “Ọmọ-Aládé Alaafia”
-
-
6 Euferate ni odò ti Abrahamu ati idile rẹ̀ là kọja lati bọ́ sinu Ilẹ Ileri naa. Nigba ti ó ń la odò naa kọja, Abrahamu wà lailọmọ, bi o tilẹ jẹ pe o ti di ẹni ọdun 75 nigba naa, ti aya rẹ̀ si ti kọja igba ọmọ bibi. (Genesisi 12:1-5) Sibẹ, loju ipo ti ó yatọ patapata bẹẹ, Ọlọrun wi fun Abrahamu onigbọran pe: “Gbojuwo oke ọ̀run nisinsinyi, ki o si ka irawọ bi iwọ ba lè ka wọn: . . . Bẹẹ ni iru-ọmọ rẹ yoo ri.”—Genesisi 15:2-5.
7. (a) Ki ni a ń pe majẹmu yii? (b) Ní ọdun wo ni ó bẹrẹsii ṣiṣẹ ati pẹlu iṣẹlẹ wo ninu igbesi-aye Abrahamu? (c) O tó ọdun mélòó ki a tó wá dá majẹmu Ofin pẹlu orilẹ-ede Israeli?
7 Majẹmu naa ti Jehofa dá pẹlu “ọ̀rẹ́” rẹ̀ ni a pè ní majẹmu Abrahamu. Majẹmu naa bẹrẹsii ṣiṣẹ ní 1943 B.C.E. nigba ti Abrahamu ṣegbọran si awọn ohun ti majẹmu Ọlọrun beere fun ti ó re odò Euferate kọja nigba ti ó ń lọ si Ilẹ Ileri naa. Ní ọdun yẹn Jehofa Ọlọrun wá sabẹ iṣẹ aigbọdọmaṣe lati bukun Abrahamu alailọmọ pẹlu “iru-ọmọ.” Ofin ti ó jẹ́ ti majẹmu naa ti a ṣe pẹlu orilẹ-ede Israeli ní Oke Sinai wá di eyi ti ó wà ní 430 ọdun lẹhin naa, ní 1513 B.C.E.—Genesisi 12:1-7; Eksodu 24:3-8.
-