ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Majẹmu Ọlọrun Pẹlu “Ọ̀rẹ́” Rẹ̀ Ti Ṣanfaani fun Araadọta Ọkẹ Nisinsinyi
    Àìléwu Kárí-Ayé Labẹ “Ọmọ-Aládé Alaafia”
    • 3, 4. (a) Ki ni ó ṣakawe idiwọn giga ti Jehofa gbekari igbagbọ ati igbẹkẹle ti Abrahamu ní ninu rẹ̀? (b) Pẹlu awọn ọ̀rọ̀ wo ni Jehofa fi mu itolẹsẹẹsẹ ọ̀rọ̀ rẹ̀ ninu Isaiah 41:8 wá sí otente giga nla?

      3 Ọkunrin onigbagbọ ati agbegbeesẹ yẹn wá lati ilu Uri ti awọn ará Kaldea, oun si ni ẹni ti a kọkọ pè ní Heberu. (Genesisi 14:13) Idanimọ yii ni a wá lò fun awọn atọmọdọmọ rẹ̀ ti orilẹ-ede Israeli. (Filippi 3:5) Ní oju iwoye sisọ Abrahamu di ọ̀rẹ́ rẹ̀, Jehofa Ọlọrun tun mú un wọ inu diẹ ninu awọn ọran aṣiri Rẹ̀. Eyi ni ohun ti a kọ sinu Genesisi 18:​17-⁠19 sì fihan.

  • Majẹmu Ọlọrun Pẹlu “Ọ̀rẹ́” Rẹ̀ Ti Ṣanfaani fun Araadọta Ọkẹ Nisinsinyi
    Àìléwu Kárí-Ayé Labẹ “Ọmọ-Aládé Alaafia”
    • 6 Euferate ni odò ti Abrahamu ati idile rẹ̀ là kọja lati bọ́ sinu Ilẹ Ileri naa. Nigba ti ó ń la odò naa kọja, Abrahamu wà lailọmọ, bi o tilẹ jẹ pe o ti di ẹni ọdun 75 nigba naa, ti aya rẹ̀ si ti kọja igba ọmọ bibi. (Genesisi 12:​1-⁠5) Sibẹ, loju ipo ti ó yatọ patapata bẹẹ, Ọlọrun wi fun Abrahamu onigbọran pe: “Gbojuwo oke ọ̀run nisinsinyi, ki o si ka irawọ bi iwọ ba lè ka wọn: . . . Bẹẹ ni iru-ọmọ rẹ yoo ri.”​—⁠Genesisi 15:​2-⁠5.

      7. (a) Ki ni a ń pe majẹmu yii? (b) Ní ọdun wo ni ó bẹrẹsii ṣiṣẹ ati pẹlu iṣẹlẹ wo ninu igbesi-aye Abrahamu? (c) O tó ọdun mélòó ki a tó wá dá majẹmu Ofin pẹlu orilẹ-ede Israeli?

      7 Majẹmu naa ti Jehofa dá pẹlu “ọ̀rẹ́” rẹ̀ ni a pè ní majẹmu Abrahamu. Majẹmu naa bẹrẹsii ṣiṣẹ ní 1943 B.C.E. nigba ti Abrahamu ṣegbọran si awọn ohun ti majẹmu Ọlọrun beere fun ti ó re odò Euferate kọja nigba ti ó ń lọ si Ilẹ Ileri naa. Ní ọdun yẹn Jehofa Ọlọrun wá sabẹ iṣẹ aigbọdọmaṣe lati bukun Abrahamu alailọmọ pẹlu “iru-ọmọ.” Ofin ti ó jẹ́ ti majẹmu naa ti a ṣe pẹlu orilẹ-ede Israeli ní Oke Sinai wá di eyi ti ó wà ní 430 ọdun lẹhin naa, ní 1513 B.C.E.​—⁠Genesisi 12:​1-⁠7; Eksodu 24:​3-⁠8.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́