-
“Ẹ Jọ̀wọ́, Ẹ Fetí sí Àlá Tí Mo Lá”Ilé Ìṣọ́—2014 | August 1
-
-
Jósẹ́fù ò mọ ohun tí wọ́n ń gbèrò lọ́kàn, ó lè máa rò ó pé bóyá àwọn á tiẹ̀ rẹ́ lọ́tẹ̀ yìí. Àmọ́ ibi tó fojú sí ọ̀nà ò gba bẹ̀. Ńṣe làwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ṣùrù bò ó, tí wọ́n sì fìbínú bọ́ ẹ̀wù tí bàbá rẹ̀ fún un kúrò lọ́rùn rẹ̀. Àfi jùà! Ni wọ́n gbé e sọ sínú kòtò náà! Bí Jósẹ́fù ṣe ń pa rìdàrìdà nínú kòtò yẹn ló ń sapá láti pọ́n ògiri náà pa dà sókè, ṣùgbọ́n kò ṣeé ṣe. Ojú ọ̀run nìkan ló ń rí, ó sì ń gbọ́ ohùn àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ díẹ̀díẹ̀. Ó bẹ̀rẹ̀ sí i bẹ̀ wọ́n pé kí wọ́n ṣàánú òun àmọ́ wọn ò dá a lóhùn. Lẹ́yìn ìyẹn, wọ́n dáná, wọ́n jẹun, wọ́n tún nu ẹnu nù. Nígbà tí wọ́n rí i pé Rúbẹ́nì ò sí láàárín àwọn, wọ́n tún gbèrò láti pa á àmọ́ Júdà dábàá pé kàkà káwọn pa á, á dáa káwọn kúkú tà á fáwọn oníṣòwò tó bá kọjá. Ìlú Dótánì ò jìnnà sí ọ̀nà táwọn oníṣòwò tó ń lọ sí ilẹ̀ Íjíbítì máa ń gbà kọjá, torí náà, kò pẹ́ táwọn oníṣòwò ìlú Mídíánì àti àwọn ọmọ Íṣímáẹ́lì fi gba ibẹ̀ kọjá. Kí Rúbẹ́nì tó pa dà dé, wọ́n ti ta àbúrò wọn sóko ẹrú fún ogún ṣékélì péré.b—Jẹ́nẹ́sísì 37:23-28; 42:21.
Jósẹ́fù máa ń ṣe ohun tó tọ́, ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ kórìíra rẹ̀
-
-
“Ẹ Jọ̀wọ́, Ẹ Fetí sí Àlá Tí Mo Lá”Ilé Ìṣọ́—2014 | August 1
-
-
b Ìwádìí kan tí wọ́n ṣe fi hàn pé òótọ́ pọ́ńbélé ni ohun tó wà nínú Bíbélì yẹn. Àwọn àkájọ ìwé tí wọ́n kọ lásìkò yẹn fi hàn pé ogún ṣékélì ni iye tí wọ́n ń ta ẹrú nílẹ̀ Íjíbítì.
-