-
Kí Ni Ìsinmi Ọlọ́run?Ilé Ìṣọ́—2011 | July 15
-
-
1, 2. Kí la lè rí kọ́ nínú Jẹ́nẹ́sísì 2:3, àwọn ìbéèrè wo la sì máa dáhùn?
NÍNÚ Jẹ́nẹ́sísì orí kìíní, a kẹ́kọ̀ọ́ pé Ọlọ́run fi ọjọ́ mẹ́fà dá ayé kí èèyàn lè máa gbé inú rẹ̀. Èyí kì í ṣe ọjọ́ oníwákàtí mẹ́rìnlélógún o; ọjọ́ kọ̀ọ̀kan gùn ju bẹ́ẹ̀ lọ. Ní ìparí ọjọ́ ìṣẹ̀dá kọ̀ọ̀kan, Bíbélì sọ pé: “Alẹ́ sì wá wà, òwúrọ̀ sì wá wà.” (Jẹ́n. 1:5, 8, 13, 19, 23, 31) Àmọ́, nígbà tó di ọjọ́ keje, Bíbélì sọ pé: “Ọlọ́run sì tẹ̀ síwájú láti bù kún ọjọ́ keje, ó sì ṣe é ní ọlọ́wọ̀, nítorí pé inú rẹ̀ ni ó ti ń sinmi kúrò nínú gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ tí Ọlọ́run ti dá.”—Jẹ́n. 2:3.
2 Ǹjẹ́ o kíyè sí i pé gbólóhùn tó sọ nǹkan téèyàn ń ṣe lọ́wọ́ tí kò sì tíì parí rẹ̀ ni Bíbélì lò? Ó sọ pé, Ọlọ́run “ti ń sinmi.” Èyí tó túmọ̀ sí pé nígbà tí Mósè kọ ìwé Jẹ́nẹ́sísì ní ọdún 1513 ṣáájú Sànmánì Kristẹni ọjọ́ keje tí Bíbélì pè ní “ọjọ́” ìsìnmí Ọlọ́run ṣì ń bá a nìṣó. Títí di báyìí ńkọ́, ṣé ìsinmi Ọlọ́run ṣì ń bá a nìṣó? Bó bá rí bẹ́ẹ̀, ǹjẹ́ a lè wọnú ìsinmi rẹ̀? Ó ṣe pàtàkì pé ká mọ ìdáhùn àwọn ìbéèrè yìí.
-
-
Kí Ni Ìsinmi Ọlọ́run?Ilé Ìṣọ́—2011 | July 15
-
-
5. Kí ni Jèhófà fẹ́ lo ọjọ́ keje fún, ìgbà wo sì ni ilẹ̀ ayé máa rí bí Ọlọ́run ṣe fẹ́ kó rí?
5 Ká tó lè dáhùn ìbéèrè yẹn, ó ṣe pàtàkì ká rántí ohun tí Jèhófà fẹ́ lo ọjọ́ keje fún. Ìwé Jẹ́nẹ́sísì 2:3 ṣàlàyé pé: “Ọlọ́run sì tẹ̀ síwájú láti bù kún ọjọ́ keje, ó sì ṣe é ní ọlọ́wọ̀.” Ọlọ́run ‘ṣe ọjọ́ yẹn ní ọlọ́wọ̀,’ èyí tó túmọ̀ sí pé Jèhófà ya ọjọ́ náà sí mímọ́ tàbí pé ó yà á sọ́tọ̀ kó bàa lè lò ó láti ṣe àṣeparí ohun tó fẹ́ kí ilẹ̀ ayé jẹ́. Kí ni Ọlọ́run fẹ́ kí ilẹ̀ ayé jẹ́? Ó fẹ́ kó jẹ́ ibi tí àwọn ọkùnrin àti obìnrin onígbọràn á máa gbé tí wọ́n á máa bójú tó, tí wọ́n á sì máa tọ́jú gbogbo ohun alààyè tó wà níbẹ̀. (Jẹ́n. 1:28) Ìdí rẹ̀ nìyẹn tí Jèhófà Ọlọ́run àti Jésù Kristi tó jẹ́ “Olúwa sábáàtì” fi “ń bá a nìṣó ní ṣíṣiṣẹ́ títí di ìsinsìnyí.” (Mát. 12:8) Ọjọ́ ìsinmi Ọlọ́run á máa bá a nìṣó títí dìgbà tí ilẹ̀ ayé a fi rí bí Ọlọ́run ṣe fẹ́ kó rí ní òpin Ẹgbẹ̀rún Ọdún Ìṣàkóso Kristi.
-