-
Ohun Kan Tó Níye Lórí Ju Àwọn Ìṣúra Íjíbítì LọIlé Ìṣọ́—2002 | June 15
-
-
Bá A Ṣe Tọ́ Ọ Dàgbà àti Ìmọ̀ Ẹ̀kọ́ Tó Gbà
Jókébédì “gbé ọmọ náà, ó sì ṣètọ́jú rẹ̀. Ọmọ náà sì dàgbà. Lẹ́yìn náà, ó mú un wá fún ọmọbìnrin Fáráò, ó sì tipa báyìí di ọmọkùnrin rẹ̀.” (Ẹ́kísódù 2:9, 10) Bíbélì kò sọ bí àkókò tí Mósè lò lọ́dọ̀ àwọn òbí rẹ̀ ṣe gùn tó. Àwọn kan sọ pé ó ní láti wà níbẹ̀ ó kéré tán títí di ìgbà tí wọ́n fi já a lẹ́nu ọmú—ìyẹn ọdún méjì sí mẹ́ta—àmọ́ ó ṣeé ṣe kó gùn jù bẹ́ẹ̀ lọ. Ẹ́kísódù kò sọ ju pé ó “dàgbà” lọ́dọ̀ àwọn òbí rẹ̀, èyí ò sì tọ́ka sí iye ọdún kan pàtó. Bó ti wù kó rí, ó dájú pé Ámúrámù àti Jókébédì ti ní láti lo àkókò yẹn láti jẹ́ kí ọmọ wọn mọ̀ pé Hébérù lòun, wọ́n á sì kọ́ ọ nípa Jèhófà pẹ̀lú. Ó dìgbẹ̀yìn ká tó mọ bí wọ́n ṣe kẹ́sẹ̀ járí tó nínú gbígbin ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ fún òdodo sọ́kàn Mósè.
-
-
Ohun Kan Tó Níye Lórí Ju Àwọn Ìṣúra Íjíbítì LọIlé Ìṣọ́—2002 | June 15
-
-
[Àpótí tó wà ní ojú ìwé 11]
Iṣẹ́ Abánitọ́mọ
Àwọn ìyá ló máa ń fún àwọn ọmọ wọn lọ́yàn mu. Àmọ́, ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́jinlẹ̀ nì, Brevard Childs, sọ nínú ìwé Journal of Biblical Literature pé, “nígbà mìíràn, àwọn ìdílé ọ̀tọ̀kùlú [ìhà Àárín Gbùngbùn Ìlà Oòrùn] máa ń háyà abánitọ́mọ. Àṣà yìí tún wọ́pọ̀ níbi tí ìyá náà ò bá ti lè tọ́jú ọmọ rẹ̀ tàbí níbi tí wọn ò bá ti mọ ìyá tó bí ọmọ náà. Ẹrù iṣẹ́ abánitọ́mọ náà ni pé kó tọ́jú ọmọ náà, kó sì máa fún un lọ́yàn mu láàárín àkókò tí wọ́n jọ fọwọ́ sí náà.” Àwọn ìwé kan tá a fi òrépèté ṣe láti ìhà Àárín Gbùngbùn Ìlà Oòrùn ṣì wà títí di báyìí, tó sọ̀rọ̀ nípa àdéhùn iṣẹ́ pẹ̀lú àwọn abánitọ́mọ. Àkọsílẹ̀ wọ̀nyí jẹ́rìí sí àṣà tó gbòde láti sáà àwọn ẹ̀yà Sumer títí di sáà àwọn Hélénì ní Íjíbítì. Àwọn apá tó wọ́pọ̀ jù nínú àwọn àkọsílẹ̀ wọ̀nyí ni ohun tí ẹnì kọ̀ọ̀kan tí ọ̀ràn kàn sọ, irú bí àkókò àdéhùn náà ti máa gùn tó, bí iṣẹ́ náà ṣe máa rí, ọ̀rọ̀ nípa oúnjẹ, owó ìtanràn tí ẹnì kan kò bá mú àdéhùn rẹ̀ ṣẹ, owó iṣẹ́, àti bí wọ́n á ṣe máa san owó náà. Ọ̀gbẹ́ni Childs ṣàlàyé pé, ohun tó sábà máa ń ṣẹlẹ̀ ni pé “iṣẹ́ ìtọ́jú yìí máa ń gbà tó ọdún méjì sí mẹ́ta. Inú ilé abánitọ́mọ ló ti máa tọ́jú ọmọ náà, àmọ́ yóò máa mú ọmọ ọ̀hún lọ sọ́dọ̀ ẹni tó ní in lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan fún àyẹ̀wò.”
-