-
“Mo Mọ Ìrora Tí Wọ́n Ń Jẹ Ní Àmọ̀dunjú”Ilé Ìṣọ́—2009 | March 1
-
-
Lọ́jọ́ kan, nígbà tí Mósè ń bójú tó àwọn àgùntàn, ó rí ohun àràmérìíyìírí kan, ó rí iná lára igi ẹlẹ́gùn-ún kan àmọ́ igi ẹlẹ́gùn-ún náà ‘kò jó.’ (Ẹsẹ 2) Ó sún mọ́ igi tíná bò náà kó lè mohun tó fà á. Jèhófà lo ọ̀kan lára àwọn áńgẹ́lì láti bá Mósè sọ̀rọ̀ láti àárín igi tíná wá lára ẹ, ó sọ pé: “Má ṣe sún mọ́ ìhín. Bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí pé ilẹ̀ mímọ́ ni ibi tí ìwọ dúró sí.” (Ẹsẹ 5) Rò ó wò ná, torí pé igi tíná ń jó lára ẹ̀ náà fi hàn pé Ọlọ́run mímọ́ wà nítòsí, ilẹ̀ ibi tí igi náà wà di mímọ́!
-
-
“Mo Mọ Ìrora Tí Wọ́n Ń Jẹ Ní Àmọ̀dunjú”Ilé Ìṣọ́—2009 | March 1
-
-
Ìyọ́nú Ọlọ́run jẹ́ ká nírètí pé nǹkan ṣì ń bọ̀ wá dáa. Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ rẹ̀, àwa èèyàn aláìpé lè máa hùwà níbàámu pẹ̀lú ìlànà òdodo rẹ̀ tó jẹ́ mímọ́, ìyẹn sì lè jẹ́ kí Ọlọ́run yọ́nú sí wa. (1 Pétérù 1:15, 16) Ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Mósè níbi tíná ti ń jó lára igi ẹlẹ́gùn-ún yẹn tu obìnrin kan tó jẹ́ Kristẹni nínú, torí pé ọjọ́ pẹ́ tó ti ń bá ẹ̀dùn ọkàn àti ìsoríkọ́ yí. Obìnrin náà sọ pé: “Tí Jèhófà bá lè sọ ilẹ̀ tó dọ̀tí di mímọ́, á jẹ́ pé tèmi náà ṣì lè dáa nìyẹn. Ríronú lọ́nà yìí ti ràn mí lọ́wọ́ gan-an ni.”
-