-
Ó Mọbi Tágbára Wa MọIlé Ìṣọ́—2009 | June 1
-
-
Tó bá ṣẹlẹ̀ pé ẹnì kan ò tiẹ̀ wá lágbára láti ra àwọn ẹyẹ méjì yẹn ńkọ́? Òfin náà sọ pé: “Nígbà náà, kí ó mú ìdá mẹ́wàá òṣùwọ̀n eéfà [kọ́ọ́bù mẹ́jọ tàbí mẹ́sàn-án] ìyẹ̀fun kíkúnná fún ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ wá, gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti dá.” (Ẹsẹ 11) Jèhófà gba àwọn tálákà láyè lábẹ́ Òfin láti rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láìlo ẹ̀jẹ̀.a Torí pé ẹnì kan jẹ́ tálákà nílẹ̀ Ísírẹ́lì ò ní kó má lè rúbọ tàbí kò máà láǹfààní láti wà lálàáfíà pẹ̀lú Ọlọ́run.
-
-
Ó Mọbi Tágbára Wa MọIlé Ìṣọ́—2009 | June 1
-
-
a Ohun tó jẹ́ kí wọ́n máa lo ẹran láti fi rúbọ ni ìtóye ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, èyí tí Ọlọ́run kà sóhun mímọ́. (Léfítíkù 17:11) Ṣéyẹn wá túmọ̀ sí pé ìyẹ̀fun táwọn tálákà fi ń rúbọ ò já mọ́ nǹkan kan nìyẹn? Rárá o. Ó dájú pé Jèhófà mọrírì ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀ àti ẹ̀mí ìmúratán táwọn tó fi ìyẹ̀fun rúbọ ní. Yàtọ̀ síyẹn, ẹ̀jẹ̀ àwọn ẹran tí wọ́n bá fi rúbọ sí Ọlọ́run ní Ọjọ́ Ètùtù tí wọ́n máa ń ṣe lọ́dọọdún máa kó ẹ̀ṣẹ̀ tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà dá pa pọ̀, títí kan tàwọn tálákà.—Léfítíkù 16:29, 30.
-