-
“Ibi Tí O Bá Lọ Ni Èmi Yóò Lọ”Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Ìgbàgbọ́ Wọn
-
-
16-18. (a) Báwo ni Rúùtù ṣe fi hàn pé òun ní ìfẹ́ tí kì í yẹ̀? (b) Kí ni ìtàn Rúùtù fi kọ́ wa nípa ìfẹ́ tí kì í yẹ̀? (Tún wo àwòrán àwọn obìnrin méjèèjì.)
16 Bí Rúùtù ṣe ń bá Náómì sọ̀rọ̀ lójú ọ̀nà tó dá páropáro yẹn, kò ṣiyè méjì rárá nípa ohun tó fẹ́ ṣe. Ó nífẹ̀ẹ́ Náómì dénú, ó sì tún nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run tí Náómì ń sìn. Torí náà, Rúùtù sọ fún Náómì pé: “Má rọ̀ mí láti pa ọ́ tì, láti padà lẹ́yìn rẹ; nítorí ibi tí o bá lọ ni èmi yóò lọ, ibi tí o bá sì sùn mọ́jú ni èmi yóò sùn mọ́jú. Àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi. Ibi tí o bá kú sí ni èmi yóò kú sí, ibẹ̀ sì ni ibi tí a ó sin mí sí. Kí Jèhófà ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi, kí ó sì fi kún un, bí ohunkóhun yàtọ̀ sí ikú bá ya èmi àti ìwọ.”—Rúùtù 1:16, 17.
“Àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi”
17 Mánigbàgbé ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Rúùtù sọ yìí. Kódà, ní ẹgbẹ̀rún mẹ́ta [3,000] ọdún lẹ́yìn tí Rúùtù ti kú, àwọn èèyàn ṣì ń rántí ohun tó sọ. Àwọn ohun tó sọ yìí jẹ́ ká mọ̀ pé ó ní ànímọ́ kan tó fani mọ́ra gan-an, ìyẹn ni ìfẹ́ tí kì í yẹ̀. Okùn ìfẹ́ yẹn yi débi pé Rúùtù ṣe tán láti bá Náómì dé ibikíbi tó bá ń lọ. Ikú nìkan ló lè yà wọ́n. Àwọn èèyàn Náómì ni yóò di èèyàn Rúùtù torí ó ṣe tán láti fi ilé àti ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀, tó fi mọ́ àwọn òrìṣà ilẹ̀ Móábù. Rúùtù ò dà bí Ópà, torí tọkàntọkàn ló fi sọ pé Jèhófà tó jẹ́ Ọlọ́run Náómì ni òun fẹ́ kó jẹ́ Ọlọ́run òun.a
-
-
“Ibi Tí O Bá Lọ Ni Èmi Yóò Lọ”Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Ìgbàgbọ́ Wọn
-
-
a Ó yẹ ká kíyè sí i pé Rúùtù kò kàn lo orúkọ oyè náà “Ọlọ́run” bí ọ̀pọ̀ àwọn àjèjì ì bá ti ṣe. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó lo orúkọ tí Ọlọ́run ń jẹ́ gan-an, ìyẹn Jèhófà. Ìtumọ̀ Bíbélì kan tiẹ̀ sọ pé: “Nípa báyìí, ẹni tó kọ ìwé Rúùtù jẹ́ kó ṣe kedere pé bí Rúùtù tilẹ̀ jẹ́ àjèjì, Ọlọ́run tòótọ́ ló ń sìn.”—The Interpreter’s Bible.
-