-
“Ibi Tí O Bá Lọ Ni Èmi Yóò Lọ”Ilé Ìṣọ́—2012 | July 1
-
-
Bí Rúùtù ṣe ń wo Náómì nígbà tó ń bá a sọ̀rọ̀ lójú ọ̀nà tó dá páropáro yẹn, kò sí ìyè méjì kankan lọ́kàn rẹ̀ nípa ohun tó fẹ́ ṣe. Ó nífẹ̀ẹ́ Náómì jinlẹ̀-jinlẹ̀ látọkàn wá àti Ọlọ́run tí Náómì ń sìn. Ìyẹn ló ṣe sọ fún Náómì pé: “Má rọ̀ mí láti pa ọ́ tì, láti padà lẹ́yìn rẹ; nítorí ibi tí o bá lọ ni èmi yóò lọ, ibi tí o bá sì sùn mọ́jú ni èmi yóò sùn mọ́jú. Àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi. Ibi tí o bá kú sí ni èmi yóò kú sí, ibẹ̀ sì ni ibi tí a ó sin mí sí. Kí Jèhófà ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi, kí ó sì fi kún un, bí ohunkóhun yàtọ̀ sí ikú bá ya èmi àti ìwọ.”—Rúùtù 1:16, 17.
Ọ̀rọ̀ tí Rúùtù sọ yẹn fa kíki gan-an débi pé àwọn èèyàn ṣì ń rántí rẹ̀ láti nǹkan bí ẹgbẹ̀rún ọdún mẹ́ta [3,000] sẹ́yìn tó ti kú. Ọ̀rọ̀ yẹn jẹ́ ká mọ̀ pé Rúùtù níwà kan tó fani mọ́ra gan-an, ìyẹn ìfẹ́ tí kì í yẹ̀. Okùn ìfẹ́ yẹn yi, ó sì lágbára gan-an débi pé ibikíbi tí Náómì bá ń lọ Rúùtù yóò bá a débẹ̀. Ikú nìkan ló lè yà wọ́n. Ní báyìí, àwọn èèyàn Náómì ni yóò di èèyàn rẹ̀, torí Rúùtù ti múra tán láti fi gbogbo ohun tó mọ̀ ní Móábù sílẹ̀, títí kan àwọn òrìṣà ilẹ̀ Móábù. Rúùtù kò dà bí Ópà, torí tọkàntọkàn ló fi sọ pé Jèhófà, ìyẹn Ọlọ́run tí Náómì ń sìn, ni Ọlọ́run ti òun náà fẹ́ máa sìn.b
-
-
“Ibi Tí O Bá Lọ Ni Èmi Yóò Lọ”Ilé Ìṣọ́—2012 | July 1
-
-
b Ó wúni lórí láti rí i pé Rúùtù kò kàn lo orúkọ òye náà “Ọlọ́run” nìkan bí ọ̀pọ̀ àwọn ará ilẹ̀ òkèèrè ṣe sábà máa ń ṣe. Ó tún lo orúkọ Ọlọ́run gan-an, ìyẹn Jèhófà. Ìwé náà,The Interpreter’s Bible sọ pé: “Òǹkọ̀wé Bíbélì yẹn wá jẹ́ kó ṣe kedere pé Ọlọ́run tòótọ́ ni ará ilẹ̀ òkèèrè yìí ń sìn.”
-