-
Jerúsálẹ́mù àti Tẹ́ńpìlì Sólómọ́nìWo “Ilẹ̀ Dáradára” Náà
-
-
Orí òkè tó ga tó àádọ́ta lé lẹ́ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin [750] mítà láàárín ọ̀wọ́ àwọn òkè Jùdíà ni Jerúsálẹ́mù wà. Bíbélì sọ̀rọ̀ nípa ‘ìgafíofío’ rẹ̀, ó sì sọ pé àwọn olùjọsìn ń “gòkè lọ” síbẹ̀. (Sm 48:2; 122:3, 4) Àfonífojì ló yí ìlú ìgbàanì náà ká: Àfonífojì Hínómù wà ní ìwọ̀ oòrùn àti àríwá, àfonífojì olójú ọ̀gbàrá Kídírónì sì wà ní ìlà oòrùn. (2Ọb 23:10; Jer 31:40) Ojúsun omi Gíhónìa tó wà ní Àfonífojì Kídírónì àti Ẹ́ń-rógélì tó wà ní gúúsù ló ń pèsè omi mímu tí kò níyọ̀, èyí sì ṣe pàtàkì nígbà táwọn ọ̀tá bá ń gbéjà kò wọ́n.—2Sa 17:17.
-
-
Jerúsálẹ́mù àti Tẹ́ńpìlì Sólómọ́nìWo “Ilẹ̀ Dáradára” Náà
-
-
Ẹnubodè Òkìtì-eérú (Àpáàdì) (Ẹlẹ́bọ́tọ)
-