-
Ìbẹ̀wò Kan Tó Lérè Púpọ̀Ilé Ìṣọ́—1999 | July 1
-
-
Ọgbọ́n Sólómọ́nì àti aásìkí ìjọba rẹ̀ wú ọbabìnrin Ṣébà lórí gan-an ni débi pé “kò wá sí ẹ̀mí kankan mọ́ nínú rẹ̀.” (1 Ọba 10:4, 5) Àwọn kan túmọ̀ gbólóhùn ọ̀rọ̀ yìí sí pé ọbabìnrin náà “sé èémí.” Ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́jinlẹ̀ kan tilẹ̀ sọ pé ó dákú! Èyí ó wù kó jẹ́, ẹnu ṣáà ya ọbabìnrin náà sí ohun tó rí àti èyí tó gbọ́. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ Sólómọ́nì ní aláyọ̀ nítorí àǹfààní tí wọ́n ní láti gbọ́ ọgbọ́n ọba yìí, ó sì fi ìbùkún fún Jèhófà fún gbígbé tó gbé Sólómọ́nì sórí ìtẹ́. Lẹ́yìn náà ó wá fún ọba ní ẹ̀bùn olówó iyebíye, àpapọ̀ iye owó wúrà nìkan ń lọ sí nǹkan bí ogójì mílíọ̀nù dọ́là táa ba fi bí nǹkan ṣe rí lónìí ṣírò rẹ̀. Sólómọ́nì náà fún ọbabìnrin náà lẹ́bùn, ó fún un ní “gbogbo ohun tí ó jẹ́ inú dídùn rẹ̀, èyí tí òun béèrè.”c—1 Ọba 10:6-13.
-
-
Ìbẹ̀wò Kan Tó Lérè Púpọ̀Ilé Ìṣọ́—1999 | July 1
-
-
c Àwọn kan gbà pé ohun tí gbólóhùn yìí ń sọ ni pé ọbabìnrin náà ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú Sólómọ́nì. Àwọn ìtàn àtẹnudẹ́nu tilẹ̀ sọ pé wọ́n bí ọmọkùnrin kan. Àmọ́, kò sí ẹ̀rí tó ti èyíkéyìí nínú rẹ̀ lẹ́yìn.
-