-
Ó Gbèjà Àwọn Èèyàn Ọlọ́runIlé Ìṣọ́—2011 | October 1
-
-
Ọkùnrin kan tó ń jẹ́ Hámánì di ẹni ńlá láàfin Ahasuwérúsì. Ọba yan Hámánì sí ipò olórí ìjọba, ó fi ṣe olórí agbani-nímọ̀ràn rẹ̀, tí ìyẹn sì wá mú kó wà nípò kejì ní ilẹ̀ ọba náà. Ọba tiẹ̀ tún pàṣẹ pé, gbogbo ẹni tó bá rí olóyè pàtàkì yìí ní láti tẹrí ba fún un. (Ẹ́sítérì 3:1-4) Ìṣòro ni àṣẹ yẹn jẹ́ fún Módékáì. Ó mọ̀ pé ó yẹ kí òun ṣègbọràn sí ọba, àmọ́ kò gbọ́dọ̀ ṣàìgbọràn sí Ọlọ́run nítorí òfin ọba. Ṣẹ́ ẹ rí i, “ọmọ Ágágì” ni Hámánì. Èyí fi hàn pé ọmọ ìran Ágágì tó jẹ́ ọba Ámálékì tí Sámúẹ́lì wòlíì Ọlọ́run pa ni ọ̀gbẹ́ni yìí. (1 Sámúẹ́lì 15:33) Àwọn ọmọ Ámálékì yìí burú débi pé, wọ́n sọ ara wọn di ọ̀tá Jèhófà àtàwọn ọmọ Ísírẹ́lì. Èyí sì mú káwọn ọmọ Ámálékì jẹ́ ẹni ìparun lójú Ọlọ́run.b (Diutarónómì 25:19) Báwo ni Júù kan tó jẹ́ olóòótọ́ á ṣe máa tẹrí ba fún olóyè kan tó jẹ́ ọmọ Ámálékì? Módékáì kò ní ṣe bẹ́ẹ̀ láé. Ó dúró lórí ìpinnu rẹ̀ pé òun kò ní tẹrí ba fún un. Títí dòní, àwọn ọkùnrin àtobìnrin tó ní ìgbàgbọ́ kò kọ ohun tí ì bá ṣẹlẹ̀ sí ẹ̀mí wọn nítorí àtiṣe ohun tí ìlànà Ọlọ́run sọ pé: “Àwa gbọ́dọ̀ ṣègbọràn sí Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí olùṣàkóso dípò àwọn ènìyàn.”—Ìṣe 5:29.
-
-
Ó Gbèjà Àwọn Èèyàn Ọlọ́runIlé Ìṣọ́—2011 | October 1
-
-
b Ìgbà ayé Hesekáyà Ọba ni wọ́n pa “àṣẹ́kù” àwọn ọmọ Ámálékì, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé Hámánì wà lára àwọn tó ṣẹ́ kù nígbà yẹn.—1 Kíróníkà 4:43.
-