-
Jèhófà Mọ Iye ‘Irun Orí Rẹ’Ilé Ìṣọ́—2005 | August 1
-
-
“Fi Omijé Mi Sínú Ìgò Awọ Rẹ”
12. Báwo la ṣe mọ̀ pé Jèhófà mọ ohun tójú àwọn èèyàn rẹ̀ ń rí?
12 Kì í ṣe pé Jèhófà mọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́kọ̀ọ̀kan nìkan ni, ó tún mọ gbogbo ìpọ́njú tó ń bá ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn fínra. Àpẹẹrẹ kan ni ti ìgbà táwọn ará Íjíbítì ń pọ́n àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lójú tí wọ́n sì ń fi wọ́n ṣe ẹrú. Jèhófà sọ fún Mósè pé: “Láìsí tàbí-ṣùgbọ́n, mo ti rí ṣíṣẹ́ tí a ń ṣẹ́ àwọn ènìyàn mi tí ń bẹ ní Íjíbítì níṣẹ̀ẹ́, mo sì ti gbọ́ igbe ẹkún wọn nítorí àwọn tí ń kó wọn ṣiṣẹ́; nítorí tí mo mọ ìrora tí wọ́n ń jẹ ní àmọ̀dunjú.” (Ẹ́kísódù 3:7) Ẹ ò rí i pé ohun ìtùnú ló jẹ́ fún wa láti mọ̀ pé Jèhófà ń rí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ sí wa ó sì ń gbọ́ igbe wa nígbà tá a bá ń fara da àdánwò! Ó dájú pé kò dágunlá sáwọn ìṣòro wa.
13. Kí ló fi hàn pé àánú àwọn ìránṣẹ́ Jèhófà máa ń ṣe é gan-an?
13 Pé Jèhófà bìkítà fáwọn tó ní àjọṣe pẹ̀lú rẹ̀ la túbọ̀ rí nínú bí àánú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe máa ń ṣe é. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé orí kunkun wọn ló máa ń fa ìpọ́njú tó dé bá wọn lọ́pọ̀ ìgbà, síbẹ̀ Aísáyà kọ̀wé nípa Jèhófà pé: “Nínú gbogbo wàhálà wọn, ó jẹ́ wàhálà fún un.” (Aísáyà 63:9) Níwọ̀n bí ìwọ sì ti jẹ́ olóòótọ́ ìránṣẹ́ Jèhófà, nígbà náà, jẹ́ kó dá ọ lójú pé tí ohun kan bá ń kó ẹ̀dùn ọkàn bá ọ, ó ń kó ẹ̀dùn ọkàn bá Jèhófà náà. Ǹjẹ́ èyí kò túbọ̀ mú kó o fẹ́ láti kojú ìṣòro rẹ láìbẹ̀rù kó o sì máa ṣe gbogbo ohun tó o bá lè ṣe láti máa sìn ín nìṣó?—1 Pétérù 5:6, 7.
14. Ipò wo ni Dáfídì bá ara rẹ̀ tó mú un kọ ọ̀rọ̀ tó wà nínú Sáàmù Kẹrìndínlọ́gọ́ta?
14 Ó dá ọba Dáfídì lójú pé Jèhófà bìkítà fún òun, ó sì dùn ún pé òun wà nínú ìṣòro. Èyí hàn kedere nínú Sáàmù Kẹrìndínlọ́gọ́ta tí Dáfídì kọ nígbà tó ń sá lọ nítorí Ọba Sọ́ọ̀lù tó fẹ́ pà á. Dáfídì sá lọ sílùú Gátì, àmọ́ ẹ̀rù bà á pé àwọn Filísínì yóò mú òun tí wọ́n bá dá òun mọ̀. Ó kọ̀wé pé: “Àwọn ọ̀tá mi ń kù gìrì mọ́ mi ṣáá láti òwúrọ̀ ṣúlẹ̀, nítorí pé ọ̀pọ̀ ènìyàn ní ń fi ọkàn gíga bá mi jagun.” Nítorí ipò eléwu tí Dáfídì bá ara rẹ̀ yìí, ó yíjú sí Jèhófà. Ó wá sọ pé: “Láti òwúrọ̀ ṣúlẹ̀ ni wọ́n ń ṣe àwọn àlámọ̀rí tèmi lọ́ṣẹ́. Gbogbo ìrònú wọn ni ó lòdì sí mi fún búburú.”—Sáàmù 56:2, 5.
15. (a) Kí ni Dáfídì ní lọ́kàn nígbà tó sọ pé kí Jèhófà rọ omijé òun sínú ìgò awọ tàbí kó kọ ọ́ sínú ìwé? (b) Tá a bá ń fara da ìṣòro tó ń dán ìgbàgbọ́ wa wò, kí ló yẹ kó dá wa lójú?
15 Lẹ́yìn náà, gẹ́gẹ́ bí ohun tó wà lákọsílẹ̀ nínú Sáàmù 56:8, Dáfídì wá sọ gbólóhùn tó fani mọ́ra gan-an yìí pé: “Jíjẹ́ tí mo jẹ́ ìsáǹsá ni ìwọ alára ti ròyìn. Fi omijé mi sínú ìgò awọ rẹ. Wọn kò ha sí nínú ìwé rẹ?” Ẹ ò rí i pé bí Dáfídì ṣe ṣàpèjúwe ọ̀nà tí Jèhófà gbà ń fìfẹ́ bójú tó àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yìí wọni lọ́kàn gan-an! Tá a bá wà nínú ìdààmú, a tiẹ̀ lè máa sunkún bá a ti ń ké pe Jèhófà. Ṣebí Jésù tó jẹ́ ẹni pípé pàápàá sunkún. (Hébérù 5:7) Ó dá Dáfídì lójú pé Jèhófà ń kíyè sí òun àti pé yóò rántí ìnira òun, bí ẹni pé ó tọ́jú omi ojú òun sínú ìgò awọ tàbí pé ó kọ ọ́ sínú ìwé.d Ó tiẹ̀ ṣeé ṣe kó o máa rò ó pé omijé tìrẹ á fẹ́rẹ̀ẹ́ kún ìgò awọ náà tàbí pé yóò kún ọ̀pọ̀lọpọ̀ irú ojú ìwé bẹ́ẹ̀. Bó bá jẹ́ pé bí ìbànújẹ́ rẹ ṣe pọ̀ tó nìyẹn, ìtùnú wà. Bíbélì mú un dá wa lójú pé: “Jèhófà sún mọ́ àwọn oníròbìnújẹ́ ní ọkàn-àyà; ó sì ń gba àwọn tí a wó ẹ̀mí wọn palẹ̀ là.”—Sáàmù 34:18.
-
-
Jèhófà Mọ Iye ‘Irun Orí Rẹ’Ilé Ìṣọ́—2005 | August 1
-
-
d Láyé ọjọ́un, awọ àgùntàn, awọ ewúrẹ́ àti ti màlúù tí wọ́n ti sá gbẹ nínú oòrùn ni wọ́n fi máa ń ṣe irú àwọn ìgò awọ bẹ́ẹ̀. Inú wọn ni wọ́n máa ń rọ mílíìkì, bọ́tà, wàrà tàbí omi sí. Kódà wọ́n lè rọ òróró tàbí wáìnì sínú àwọn tí wọ́n bá sá gbẹ dáadáa.
-