-
Ta Ló Lè Dá Àwọn Tó Ń kígbe Fún Ìrànlọ́wọ́ Nídè?Ilé Ìṣọ́—2010 | August 15
-
-
14, 15. Báwo la ṣe mọ̀ pé Jésù mọ bọ́rọ̀ ṣe rí lára àwa èèyàn àti pé ó máa “dá òtòṣì tí ń kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nídè”?
14 Àwa èèyàn ẹlẹ́ṣẹ̀ wà nínú ipò tó burú jáì, a sì nílò ìrànlọ́wọ́ lójú méjèèjì. Àmọ́, a ní ìrètí. (Ka Sáàmù 72:12-14.) Jésù tó jẹ́ Sólómọ́nì Títóbi Jù ń bá wa kẹ́dùn torí pé ó mọ̀ pé aláìpé ni wá. Síwájú sí i, Jésù jìyà nítorí òdodo, Ọlọ́run sì gbà á láyè láti fojú winá àdánwò. Ìdààmú ọkàn tó bá Jésù pọ̀ débi pé “òógùn rẹ̀ sì wá dà bí ẹ̀kán ẹ̀jẹ̀ tí ń jábọ́ sí ilẹ̀”! (Lúùkù 22:44) Lẹ́yìn náà, nígbà tó wà lórí òpó igi oró, ó kígbe pé: “Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èé ṣe tí ìwọ fi ṣá mi tì?” (Mát. 27:45, 46) Pẹ̀lú gbogbo ìyà tí Jésù jẹ yìí àti bí Sátánì ṣe gbógun tì í kó lè kẹ̀yìn sí Jèhófà, kò ṣíwọ́ jíjẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà Ọlọ́run.
-
-
Ta Ló Lè Dá Àwọn Tó Ń kígbe Fún Ìrànlọ́wọ́ Nídè?Ilé Ìṣọ́—2010 | August 15
-
-
16. Kí ló mú kí Sólómọ́nì lè bá àwọn tó wà lábẹ́ àkóso rẹ̀ kẹ́dùn?
16 Torí pé Sólómọ́nì ní ọgbọ́n àti ìfòyemọ̀, kò sí àní-àní pé ó “káàánú ẹni rírẹlẹ̀.” Síbẹ̀, inú tirẹ̀ náà bà jẹ́, ó sì dojú kọ àwọn ìṣòro kan tó dà á lọ́kàn rú ní ìgbésí ayé rẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, Ámínónì tó jẹ́ ẹ̀gbọ́n Sólómọ́nì, fipá bá Támárì tó jẹ́ àbúrò rẹ̀ tí obìnrin míì bí fún bàbá wọn, lò pọ̀, Ábúsálómù tó jẹ́ iyèkan Támárì àti ẹ̀gbọ́n fún Sólómọ́nì sì pa Ámínónì nítorí ọ̀ràn yìí. (2 Sám. 13:1, 14, 28, 29) Ábúsálómù fẹ́ dìtẹ̀ gbàjọba lọ́wọ́ Dáfídì, àmọ́ ọ̀tẹ̀ náà kò kẹ́sẹ járí, Jóábù sì ṣekú pa Ábúsálómù. (2 Sám. 15:10, 14; 18:9, 14) Lẹ́yìn náà, Ádóníjà arákùnrin Sólómọ́nì náà gbìyànjú láti gba ìjọba. Ká sọ pé ó ṣàṣeyọrí ni, ẹ̀mí Sólómọ́nì ì bá lọ sí i. (1 Ọba 1:5) Ohun tó jẹ́ ká mọ̀ pé Sólómọ́nì mọ bí ìyà ṣe rí lára ni ọ̀rọ̀ tó sọ nínú àdúrà tó gbà níbi ayẹyẹ ìyàsímímọ́ tẹ́ńpìlì Jèhófà. Lórí kókó yìí, Sólómọ́nì Ọba gbàdúrà pé: “Nítorí pé olúkúlùkù wọn mọ ìyọnu àjàkálẹ̀ tirẹ̀ àti ìrora tirẹ̀ . . . Kí [ìwọ Jèhófà] sì dárí jì, kí o sì fi fún olúkúlùkù ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ọ̀nà rẹ̀.”—2 Kíró. 6:29, 30.
17, 18. Ìnira wo ni àwọn kan lára àwọn èèyàn Ọlọ́run ń kojú, kí ló sì ti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti kẹ́sẹ járí?
17 Ó lè jẹ́ ohun tó ti ṣẹlẹ̀ sí wa nígbà kan rí ló fa “ìrora” fún wa. Arábìnrin kan tó ń jẹ́ Mary,a ẹni ọgbọ̀n ọdún ó lé díẹ̀ kọ̀wé pé: “Kò sí ohun tó lè mú kí n máà láyọ̀, àmọ́ ohun tó ti ṣẹlẹ̀ sí mi kọjá máa ń mú kí ojú tì mí, ó sì máa ń kó mi ní ìríra. Inú mi á wá bà jẹ́, á sì máa ṣe mí bíi pé kí n bú sẹ́kún, bíi pé àná lọ̀rọ̀ náà ṣẹlẹ̀. Bí ọ̀rọ̀ yìí kò ṣe lọ lọ́kàn mi bọ̀rọ̀ máa ń jẹ́ kó ṣe mí bíi pé mi ò já mọ́ nǹkan kan, ẹ̀rí ọkàn sì máa ń dà mí láàmú.”
18 Ọ̀pọ̀ àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run ló lè máa ní irú èrò yìí, àmọ́ kí ló lè ràn wọ́n lọ́wọ́ láti ní okun tí wọ́n á fi lè fara dà á? Mary sọ pé: “Àwọn ọ̀rẹ́ tòótọ́ àtàwọn ará nínú ìjọ máa ń jẹ́ kí n láyọ̀. Mo máa ń gbìyànjú láti pọkàn pọ̀ sórí àwọn ohun tí Jèhófà ṣèlérí lọ́jọ́ iwájú, ó sì dá mi lójú pé igbe tí mò ń ké fún ìrànlọ́wọ́ máa di igbe ayọ̀.” (Sm. 126:5) A ní láti gbé ìrètí wa karí pípèsè tí Ọlọ́run pèsè Ọmọ rẹ̀, tó jẹ́ Alákòóso tó yàn. Bíbélì sọ tẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀ pé: “Òun yóò káàánú ẹni rírẹlẹ̀ àti òtòṣì, yóò sì gba ọkàn àwọn òtòṣì là. Yóò tún ọkàn wọn rà padà lọ́wọ́ ìnilára àti lọ́wọ́ ìwà ipá, ẹ̀jẹ̀ wọn yóò sì ṣe iyebíye ní ojú rẹ̀.” (Sm. 72:13, 14) Ọ̀rọ̀ yìí mà fini lọ́kàn balẹ̀ o!
-