-
Aásìkí Lè Dán Igbagbọ Rẹ WòIlé-Ìṣọ́nà—1993 | July 15
-
-
Nikẹhin ni mímọ̀ pe ironu oun kò tọna, Asafu sọ pe: “Bi emi bá pe, emi o fọ̀ bayii: kiyesi i, emi o ṣẹ̀ si iran awọn ọmọ rẹ. Nigba ti mo rò lati mọ eyi, ó ṣoro ni oju mi, titi mo fi lọ sinu ibi-mímọ́ Ọlọrun; nigba naa ni mo mọ igbẹhin wọn. Nitootọ iwọ gbé wọn ka ibi yíyọ̀: iwọ tì wọn ṣubu sinu iparun. Bawo ni a ti mu wọn lọ sinu idahoro yii, bi ẹni pe ni iṣẹju kan! Ibẹru ni a fi ń run wọn patapata. Bi ìgbà ti ẹnikan bá jí ni oju àlá; bẹẹni Oluwa, nigba ti iwọ bá jí, iwọ ó ṣe abuku aworan wọn.”—Orin Dafidi 73:15-20.
-
-
Aásìkí Lè Dán Igbagbọ Rẹ WòIlé-Ìṣọ́nà—1993 | July 15
-
-
Asafu wá mọ̀ pe Ọlọrun gbé awọn eniyan buburu ka “ibi yíyọ̀.” Nitori pe iwalaaye wọn yika awọn ohun ti ara, wọn wà ninu ewu rírí iṣubu ojiji. Ni igbẹhin, iku yoo lé wọn bá ni ọjọ ogbó, ti ọrọ̀ wọn ti wọn fi èrú kojọ kì yoo mu iwalaaye gigun wá fun wọn. (Orin Dafidi 49:6-12) Aásìkí wọn yoo dabi àlà kan ti ń yara kọja lọ. Idajọ òdodo tilẹ lè mú ifaṣẹ-ọba muni wá bá wọn ki ọjọ ogbó wọn tó dé bi wọn ti ń ká ohun ti wọn funrugbin. (Galatia 6:7) Niwọn bi wọn ti mọọmọ dagunla si Ẹni kanṣoṣo naa ti o lè ràn wọn lọwọ, a fi wọn silẹ lailoluranlọwọ, laisi ireti. Nigba ti Jehofa bá huwa lodi si wọn, oun yoo bojuwo “aworan” wọn—ògo ati ipo wọn—pẹlu ẹ̀gàn.
-