-
Jèhófà Ń fi Bí a ó Ṣe Máa Ka Àwọn Ọjọ́ Wa Hàn WáIlé Ìṣọ́—2001 | November 15
-
-
17. Kí ni ìpíndọ́gba gígùn ẹ̀mí àwọn èèyàn, àwọn ọdún wa sì kún fún kí ni?
17 Onísáàmù náà sọ nípa gígùn ẹ̀mí ènìyàn aláìpé, ó ní: “Nínú ara wọn, ọjọ́ àwọn ọdún wa jẹ́ àádọ́rin ọdún; bí wọ́n bá sì jẹ́ ọgọ́rin ọdún nítorí àkànṣe agbára ńlá, síbẹ̀, wíwà nìṣó wọn jẹ́ lórí ìdààmú àti àwọn ohun aṣenilọ́ṣẹ́; nítorí pé kíákíá ni yóò kọjá lọ, àwa yóò sì fò lọ.” (Sáàmù 90:10) Ìpíndọ́gba gígùn ẹ̀mí àwọn èèyàn kì í sábàá ju àádọ́rin ọdún, nígbà tí Kálébù sì jẹ́ ẹni àrùnlélọ́gọ́rin ọdún, ó sọ pé irú okun tí òun ní kò wọ́pọ̀. Àwọn kan wà tí ọ̀ràn tiwọn yàtọ̀ ṣá o, irú àwọn èèyàn bí Áárónì (123), Mósè (120), àti Jóṣúà (110). (Númérì 33:39; Diutarónómì 34:7; Jóṣúà 14:6, 10, 11; 24:29) Àmọ́ ní ti àwọn tá a forúkọ wọn sílẹ̀ láti ẹni ogún ọdún sókè, ìyẹn, ìran àwọn aláìnígbàgbọ́ tó jáde wá láti Íjíbítì, àárín ogójì ọdún ni gbogbo wọ́n kú dà nù. (Númérì 14:29-34) Lóde òní, ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè, ìpíndọ́gba gígùn ẹ̀mí àwọn èèyàn kò tíì kọjá iye tí onísáàmù náà pè é. Àwọn ọdún wa kún fún “ìdààmú àti àwọn ohun aṣenilọ́ṣẹ́.” Kíákíá ni ọdún wọ̀nyí á kọjá lọ, “àwa yóò sì fò lọ.”—Jóòbù 14:1, 2.
-
-
Jèhófà Ń fi Bí a ó Ṣe Máa Ka Àwọn Ọjọ́ Wa Hàn WáIlé Ìṣọ́—2001 | November 15
-
-
19 Àwọn ọ̀rọ̀ onísáàmù náà jẹ́ àdúrà pé kí Jèhófà jọ̀wọ́ kọ́ àwọn èèyàn rẹ̀ bí wọn yóò ṣe máa fojú ribiribi wo ọjọ́ tó kù fún wọn láyé, kí wọ́n sì máa fọgbọ́n lò ó lọ́nà tínú Ọlọ́run dùn sí. Àádọ́rin ọdún tó ṣeé ṣe kéèyàn lò láyé jẹ́ nǹkan bí ẹgbàá mẹ́tàlá dín lẹ́ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta [25,500] ọjọ́. Àmọ́ o, láìka ọjọ́ orí wa sí, ‘a kò mọ ohun tí ìwàláàyè wa lè jẹ́ lọ́la, nítorí ìkùukùu ni wá, tí ń fara hàn fún ìgbà díẹ̀ àti lẹ́yìn náà tí ń dàwátì.’ (Jákọ́bù 4:13-15) Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé “ìgbà àti ìṣẹ̀lẹ̀ tí a kò rí tẹ́lẹ̀ ni ó ń ṣẹlẹ̀ sí gbogbo” wa, a ò lè sọ bá a ṣe máa pẹ́ láyé tó. Nítorí náà, ẹ jẹ́ ká máa gbàdúrà fún ọgbọ́n láti fi kojú àdánwò, láti fi mọ bó ṣe yẹ ká máa bá àwọn èèyàn lò, àti láti lè máa sa gbogbo ipá wa nínú iṣẹ́ ìsìn Jèhófà nísinsìnyí—àní lójúmọ́ tó mọ́ yìí! (Oníwàásù 9:11; Jákọ́bù 1:5-8) Jèhófà ń tọ́ wa sọ́nà nípasẹ̀ Ọ̀rọ̀ rẹ̀, ẹ̀mí rẹ̀, àti ètò àjọ rẹ̀. (Mátíù 24:45-47; 1 Kọ́ríńtì 2:10; 2 Tímótì 3:16, 17) Lílo ọgbọ́n ń jẹ́ ká máa ‘wá Ìjọba Ọlọ́run lákọ̀ọ́kọ́,’ ká sì máa lo àwọn ọjọ́ wa lọ́nà tó ń mú ògo wá fún Jèhófà, tó sì ń mú ọkàn rẹ̀ yọ̀. (Mátíù 6:25-33; Òwe 27:11) A mọ̀ pé fífi tọkàntọkàn sìn ín kò ní mú gbogbo ìṣòro wa kúrò, àmọ́ ó dájú pé ṣíṣe bẹ́ẹ̀ ń mú ayọ̀ púpọ̀ wá.
-