-
O Lè Jẹ́ Oníwà Mímọ́ Nínú Ayé OníṣekúṣeIlé Ìṣọ́—2000 | July 15
-
-
Kí tún ni ìdí mìíràn tó fi yẹ ká ta kété sí ọ̀nà oníwàkiwà? Sólómọ́nì dáhùn pé: “Kí ìwọ má bàa fi iyì rẹ fún àwọn ẹlòmíràn, tàbí kí o fi àwọn ọdún rẹ fún ohun tí ó níkà; kí àwọn àjèjì má bàa fi agbára rẹ tẹ́ ara wọn lọ́rùn, tàbí kí àwọn nǹkan tí ìwọ fi ìrora rí gbà wà ní ilé ọmọ ilẹ̀ òkèèrè, tàbí kí o wá máa kérora ní ọjọ́ ọ̀la rẹ nígbà tí ẹran ara rẹ àti ẹ̀yà ara rẹ bá wá sí òpin.”—Òwe 5:9-11.
-
-
O Lè Jẹ́ Oníwà Mímọ́ Nínú Ayé OníṣekúṣeIlé Ìṣọ́—2000 | July 15
-
-
Ṣùgbọ́n kí ni ‘fífi àwọn ọdún wa, agbára wa, àti èso làálàá wa fún àwọn àjèjì, tàbí ọmọ ilẹ̀ òkèèrè’ wé mọ́? Ìwé kan tí a ṣèwádìí nínú rẹ̀ ṣàlàyé pé: “Ohun tí ẹsẹ wọ̀nyí ń sọ ṣe kedere: Aburú tí àìṣòótọ́ nínú ìgbéyàwó ń fà kò kéré; nítorí pé ohun téèyàn fi gbogbo ọjọ́ ayé ẹ̀ ṣiṣẹ́ fún—bí ipò, agbára, aásìkí—lè pòórá yálà nípasẹ̀ àwọn nǹkan tí obìnrin náà ń fi ìwà ọ̀kánjúà gbà tàbí nípasẹ̀ ohun tí àwọn ará àdúgbò ní kí onítọ̀hún wá san nítorí ìwà ìbàjẹ́ tó hù.” Ẹ ò rí i pé apá kì í sábàá ká ohun tí ìṣekúṣe ń dá sílẹ̀!
-