-
“Pa Àwọn Àṣẹ Mi Mọ́ Kí o Sì Máa Bá a Lọ Ní Wíwà Láàyè”Ilé Ìṣọ́—2000 | November 15
-
-
Ó tẹ̀ síwájú pé: “Wá, jẹ́ kí a mu ìfẹ́ ní àmuyó títí di òwúrọ̀; jẹ́ kí a fi àwọn ìfihàn ìfẹ́ gbádùn ara wa lẹ́nì kìíní-kejì.” Ìkésíni yẹn ju kìkì pé káwọn èèyàn méjì wulẹ̀ gbádùn oúnjẹ alẹ́ alárinrin kan pa pọ̀ lọ. Ìlérí tó ń ṣe fún un jẹ́ ti gbígbádùn ìbálòpọ̀ pa pọ̀. Lójú ọmọkùnrin yẹn ní tiẹ̀, kò sóhun tó tún lè dùn ju ìyẹn lọ! Kó lè túbọ̀ kó sí i lórí pátápátá, ló bá tún fi kún-un pé: “Nítorí ọkọ kò sí ní ilé rẹ̀; ó ti rin ìrìn àjò lọ sí ọ̀nà tí ó jìn. Ó mú àpò owó lọ́wọ́. Ọjọ́ òṣùpá àrànmọ́jú ni yóò wá sí ilé rẹ̀.” (Òwe 7:18-20) Ó fi yé e pé kó séwu fáwọn, nítorí ọkọ̀ rẹ̀ ti lọ sí àjò lọ ṣòwò, yóò sì ṣe díẹ̀ kó tó padà dé. Ẹ ò rí i pé ó mọ ọgbọ́n tí wọ́n fi ń mú ẹnì kan tó jẹ́ ọ̀dọ́ gan-an ni! “Ó ti fi ọ̀pọ̀ yanturu ìyíniléròpadà rẹ̀ ṣì í lọ́nà. Ó fi dídùn mọ̀nràn-ìn mọnran-in ètè rẹ̀ sún un dẹ́ṣẹ̀.” (Òwe 7:21) Àyàfi irú èèyàn kan tó níwà bíi ti Jósẹ́fù nìkan ló lè dènà irú ìfanimọ́ra tí ń réni lọ bí èyí. (Jẹ́nẹ́sísì 39: 9, 12) Ṣé ọ̀dọ́kùnrin yìí kúnjú ìwọ̀n?
-
-
“Pa Àwọn Àṣẹ Mi Mọ́ Kí o Sì Máa Bá a Lọ Ní Wíwà Láàyè”Ilé Ìṣọ́—2000 | November 15
-
-
“Obìnrin tí ó jẹ́ àjèjì” tí ọba rí náà ré ọ̀dọ́kùnrin náà lọ pẹ̀lú ìkésíni náà pé: “jẹ́ kí a fi àwọn ìfihàn ìfẹ́ gbádùn ara wa lẹ́nì kìíní-kejì.” Ǹjẹ́ ọ̀pọ̀ ọ̀dọ́—àgàgà àwọn ọ̀dọ́bìnrin—kọ́ ni wọ́n ti bà jẹ́ ní irú ọ̀nà yìí? Ìwọ tiẹ̀ rò ó ná: Tẹ́nì kan bá ń gbìyànjú láti mú kóo lọ́wọ́ nínú ìṣekúṣe, ṣe ojúlówó ìfẹ́ ló ní fún ọ tàbí ó kàn fẹ́ lò ẹ́ fún ète ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ lásán? Kí ló dé tí ọkùnrin kán tó nífẹ̀ẹ́ obìnrin kan tinútinú ṣe máa fipá mú un láti ba gbogbo ìdálẹ́kọ̀ọ́ Kristẹni tó ti gbà àti ẹ̀rí ọkàn rẹ̀ jẹ́? Sólómọ́nì Ọba ṣí wa létí pé “kí ọkàn-àyà rẹ má yà sí” irú àwọn ọ̀nà yẹn.
-