-
“Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
-
-
Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí baba tó fẹ́ràn ọmọ ẹ̀, Sólómọ́nì Ọba ọlọ́gbọ́n tó jẹ ní Ísírẹ́lì láyé ọjọ́un sọ pé: “Ọmọ mi, bí ìwọ yóò bá gba àwọn àsọjáde mi, tí ìwọ yóò sì fi àwọn àṣẹ tèmi ṣúra sọ́dọ̀ rẹ, láti lè dẹ etí rẹ sí ọgbọ́n, kí o lè fi ọkàn-àyà rẹ sí ìfòyemọ̀; jù bẹ́ẹ̀ lọ, bí o bá ké pe òye, tí o sì fọ ohùn rẹ jáde sí ìfòyemọ̀, bí o bá ń bá a nìṣó ní wíwá a bí fàdákà, tí o sì ń bá a nìṣó ní wíwá a kiri bí àwọn ìṣúra fífarasin, bí ọ̀ràn bá rí bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò lóye ìbẹ̀rù Jèhófà, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run gan-an.”—Òwe 2:1-5.
Ǹjẹ́ o wá rí ibi tí iṣẹ́ jíjèrè ìmọ̀ wà? Nínú àwọn ẹsẹ wọ̀nyí, ọ̀rọ̀ náà “bí o bá,” fara hàn nígbà mẹ́ta. Ó ṣe kedere pé, olúkúlùkù wa ni yóò pinnu bóyá òun yóò wá ọgbọ́n àti àwọn ìsọ̀ǹgbè rẹ̀—ìfòyemọ̀ àti òye. Ṣùgbọ́n, lákọ̀ọ́kọ́ ná, a gbọ́dọ̀ “gba” ọ̀rọ̀ ọlọgbọ́n táa kọ sínú Ìwé Mímọ́ sínú ọpọlọ wa, kí a sì wá ‘fi wọ́n ṣúra.’ Ìdí nìyẹn tó fi ṣe pàtàkì pé ká kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.
-
-
“Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
-
-
Àwọn ọ̀rọ̀ bíi “gbà,” “fi ṣúra,” “ké pe,” “bá a nìṣó ní wíwá,” “bá a nìṣó ní wíwá kiri” ló tẹ̀ lé gbólóhùn náà, “bí ó bá,” táa sọ ní àsọtúnsọ nínú àwọn ẹsẹ àkọ́kọ́ inú orí kejì ìwé Òwe. Èé ṣe tí òǹkọ̀wé yìí fi lo àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tó jẹ mọ́ ṣíṣe akitiyan níhìn-ín? Ìwé kan táa ṣèwádìí nínú rẹ̀ wí pé: “[Níhìn-ín] amòye náà ń tẹnu mọ́ bí ṣíṣaápọn nínú lílépa ọgbọ́n ti pọndandan tó.” Bẹ́ẹ̀ ni, a gbọ́dọ̀ ṣaápọn láti lépa ọgbọ́n àti àwọn ànímọ́ mìíràn tó tan mọ́ ọn—ìyẹn ni ìfòyemọ̀ àti òye.
-