-
“Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
-
-
Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí baba tó fẹ́ràn ọmọ ẹ̀, Sólómọ́nì Ọba ọlọ́gbọ́n tó jẹ ní Ísírẹ́lì láyé ọjọ́un sọ pé: “Ọmọ mi, bí ìwọ yóò bá gba àwọn àsọjáde mi, tí ìwọ yóò sì fi àwọn àṣẹ tèmi ṣúra sọ́dọ̀ rẹ, láti lè dẹ etí rẹ sí ọgbọ́n, kí o lè fi ọkàn-àyà rẹ sí ìfòyemọ̀; jù bẹ́ẹ̀ lọ, bí o bá ké pe òye, tí o sì fọ ohùn rẹ jáde sí ìfòyemọ̀, bí o bá ń bá a nìṣó ní wíwá a bí fàdákà, tí o sì ń bá a nìṣó ní wíwá a kiri bí àwọn ìṣúra fífarasin, bí ọ̀ràn bá rí bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò lóye ìbẹ̀rù Jèhófà, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run gan-an.”—Òwe 2:1-5.
-
-
“Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
-
-
Ọgbọ́n ni agbára táa fi lè lo ìmọ̀ tí Ọlọ́run fún wa dáadáa. Ohun àgbàyanu ló mà jẹ́ o, pé Bíbélì mú kí ọgbọ́n wà lárọ̀ọ́wọ́tó wa! Bẹ́ẹ̀ ni, ọ̀rọ̀ ọgbọ́n ló kúnnú ẹ̀, irú àwọn èyí táa kọ sínú ìwé Òwe àti Oníwàásù, ó sì ṣe pàtàkì pé ká dẹ etí wa sírú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí. Inú Bíbélì la tún ti rí ọ̀pọ̀ àpẹẹrẹ tó ń fi àǹfààní fífi ìlànà Ọlọ́run sílò hàn àti ewu tó wà nínú ṣíṣá wọn tì. (Róòmù 15:4; 1 Kọ́ríńtì 10:11) Fún àpẹẹrẹ, ronú nípa ìtàn Géhásì olójúkòkòrò, ìránṣẹ́ wòlíì Èlíṣà. (2 Àwọn Ọba 5:20-27) Ǹjẹ́ kò kọ́ wa ní bó ṣe bọ́gbọ́n mu tó láti yẹra fún ojúkòkòrò? Kí ni ká sọ nípa àbájáde tó bani nínú jẹ́ ní ti ìbẹ̀wò tó jọ pé kò lè fa wàhálà èyí tí Dínà ọmọbìnrin Jékọ́bù ṣe sọ́dọ̀ “àwọn ọmọbìnrin ilẹ̀” Kénáánì? (Jẹ́nẹ́sísì 34:1-31) Ǹjẹ́ a ò tipa èyí rí ìwà òmùgọ̀ tó wà nínú kíkẹ́gbẹ́ búburú?—Òwe 13:20; 1 Kọ́ríńtì 15:33.
Dídẹ etí wa sí ọgbọ́n wé mọ́ níní ìfòyemọ̀ àti òye. Gẹ́gẹ́ bí ìwé atúmọ̀ èdè náà, Webster’s Revised Unabridged Dictionary, ti sọ, ìfòyemọ̀ ni “agbára tàbí èrò inú táa fi ń dá ohun kan mọ̀ yàtọ̀ sí òmíràn.” Ìfòyemọ̀ tí Ọlọ́run ń fúnni jẹ́ agbára láti dá ohun tó tọ́ mọ̀ yàtọ̀ sí ohun tí kò tọ́, ká sì wá yan ọ̀nà tó tọ́. Àfi táa bá ‘fi ọkàn-àyà wa’ sí ìfòyemọ̀, tàbí tí a ń hára gàgà láti ní in, àìjẹ́bẹ́ẹ̀, báwo la ṣe lè dúró lójú “ọ̀nà tí ó lọ sínú ìyè”? (Mátíù 7:14; fi wé Diutarónómì 30:19, 20.) Kíkẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run àti fífi í sílò ló ń fúnni ní ìfòyemọ̀.
-