-
Máa Rìn Ní ‘Ipa Ọ̀nà Ìdúróṣánṣán’Ilé Ìṣọ́—2001 | September 15
-
-
Sólómọ́nì tọ́ka sí ìjẹ́pàtàkì òdodo. Ó sọ pé: “Àwọn nǹkan tí ó níye lórí tí ó jẹ́ ti ọlọ́rọ̀ ni ìlú lílágbára rẹ̀. Ìparun àwọn ẹni rírẹlẹ̀ ni ipò òṣì wọn. Ìgbòkègbodò olódodo ń yọrí sí ìyè; èso ẹni burúkú ń yọrí sí ẹ̀ṣẹ̀.” —Òwe 10:15, 16.
-
-
Máa Rìn Ní ‘Ipa Ọ̀nà Ìdúróṣánṣán’Ilé Ìṣọ́—2001 | September 15
-
-
Ní ìyàtọ̀ pátápátá síyẹn, yálà olódodo ní nǹkan ti ara lọ́pọ̀ yanturu tàbí níwọ̀nba, ìgbòkègbodò onídùúró-ṣánṣán rẹ̀ yóò yọrí sí ìyè. Lọ́nà wo? Ní ti pé, ohun tó ní tẹ́ ẹ lọ́rùn. Kò jẹ́ kí ipò ìṣúnná owó òun ní ohunkóhun ṣe pẹ̀lú ìdúró rere tí òun ní lọ́dọ̀ Ọlọ́run. Ì báà jẹ́ olówó ni tàbí tálákà, ipa ọ̀nà olódodo yóò mú ayọ̀ wá fún un nísinsìnyí àti ìrètí ìyè àìnípẹ̀kun lọ́jọ́ iwájú. (Jóòbù 42:10-13) Ẹni ibi kì í jàǹfààní kankan, kódà bó tiẹ̀ lówó bíi ṣẹ̀kẹ̀rẹ̀. Dípò tí ì bá fi máa dúpẹ́ nítorí ààbò tí ọrọ̀ rẹ̀ fún un, kó sì máa gbé níbàámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run, ńṣe ló ń lo ọrọ̀ rẹ̀ láti gbé ìgbésí ayé ẹ̀ṣẹ̀.
-