-
“Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
-
-
Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí baba tó fẹ́ràn ọmọ ẹ̀, Sólómọ́nì Ọba ọlọ́gbọ́n tó jẹ ní Ísírẹ́lì láyé ọjọ́un sọ pé: “Ọmọ mi, bí ìwọ yóò bá gba àwọn àsọjáde mi, tí ìwọ yóò sì fi àwọn àṣẹ tèmi ṣúra sọ́dọ̀ rẹ, láti lè dẹ etí rẹ sí ọgbọ́n, kí o lè fi ọkàn-àyà rẹ sí ìfòyemọ̀; jù bẹ́ẹ̀ lọ, bí o bá ké pe òye, tí o sì fọ ohùn rẹ jáde sí ìfòyemọ̀, bí o bá ń bá a nìṣó ní wíwá a bí fàdákà, tí o sì ń bá a nìṣó ní wíwá a kiri bí àwọn ìṣúra fífarasin, bí ọ̀ràn bá rí bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò lóye ìbẹ̀rù Jèhófà, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run gan-an.”—Òwe 2:1-5.
-
-
“Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
-
-
Dídẹ etí wa sí ọgbọ́n wé mọ́ níní ìfòyemọ̀ àti òye. Gẹ́gẹ́ bí ìwé atúmọ̀ èdè náà, Webster’s Revised Unabridged Dictionary, ti sọ, ìfòyemọ̀ ni “agbára tàbí èrò inú táa fi ń dá ohun kan mọ̀ yàtọ̀ sí òmíràn.” Ìfòyemọ̀ tí Ọlọ́run ń fúnni jẹ́ agbára láti dá ohun tó tọ́ mọ̀ yàtọ̀ sí ohun tí kò tọ́, ká sì wá yan ọ̀nà tó tọ́. Àfi táa bá ‘fi ọkàn-àyà wa’ sí ìfòyemọ̀, tàbí tí a ń hára gàgà láti ní in, àìjẹ́bẹ́ẹ̀, báwo la ṣe lè dúró lójú “ọ̀nà tí ó lọ sínú ìyè”? (Mátíù 7:14; fi wé Diutarónómì 30:19, 20.) Kíkẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run àti fífi í sílò ló ń fúnni ní ìfòyemọ̀.
Báwo la wá ṣe lè “ké pe òye”—ìyẹn ni agbára láti rí bí àwọn kókó ọ̀ràn kan ṣe sokọ́ kókó ọ̀ràn mìíràn? Lóòótọ́, ọjọ́ orí àti ìrírí jẹ́ ohun pàtàkì tó lè ràn wá lọ́wọ́ láti ní òye tó pọ̀—ṣùgbọ́n kì í ṣe ìwọ̀nyí nìkan. (Jóòbù 12:12; 32:6-12) Onísáàmù náà wí pé: “Èmi ń fi òye tí ó ju ti àwọn àgbà hùwà, nítorí pé mo ti pa àwọn àṣẹ ìtọ́ni rẹ [ìyẹn, ti Jèhófà] mọ́.” Ó tún kọ ọ́ lórin pé: “Àní ìsọdimímọ́ àwọn ọ̀rọ̀ rẹ ń fúnni ní ìmọ́lẹ̀, ó ń mú kí àwọn aláìní ìrírí lóye.” (Sáàmù 119:100, 130) Jèhófà ni “Ẹni Ọjọ́ Àtayébáyé,” òye tirẹ̀ sì ju ti gbogbo aráyé lọ fíìfíì. (Dáníẹ́lì 7:13) Ọlọ́run lè fún ẹni tí kò nírìírí ní òye, ó sì lè ràn án lọ́wọ́ láti ní ànímọ́ yẹn ju àwọn tó jù ú lọ lọ́jọ́ orí pàápàá. Nítorí náà, ó yẹ ká jẹ́ aláápọn nínú kíkẹ́kọ̀ọ́ àti fífi Bíbélì, Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, sílò.
Àwọn ọ̀rọ̀ bíi “gbà,” “fi ṣúra,” “ké pe,” “bá a nìṣó ní wíwá,” “bá a nìṣó ní wíwá kiri” ló tẹ̀ lé gbólóhùn náà, “bí ó bá,” táa sọ ní àsọtúnsọ nínú àwọn ẹsẹ àkọ́kọ́ inú orí kejì ìwé Òwe. Èé ṣe tí òǹkọ̀wé yìí fi lo àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tó jẹ mọ́ ṣíṣe akitiyan níhìn-ín? Ìwé kan táa ṣèwádìí nínú rẹ̀ wí pé: “[Níhìn-ín] amòye náà ń tẹnu mọ́ bí ṣíṣaápọn nínú lílépa ọgbọ́n ti pọndandan tó.” Bẹ́ẹ̀ ni, a gbọ́dọ̀ ṣaápọn láti lépa ọgbọ́n àti àwọn ànímọ́ mìíràn tó tan mọ́ ọn—ìyẹn ni ìfòyemọ̀ àti òye.
-