-
Ní Ọgbọ́n, Kí O Sì Gba ÌbáwíIlé Ìṣọ́—1999 | September 15
-
-
A ṣàlàyé ète táa fi kọ ìwé Òwe nínú ìnasẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀, bó ṣe bẹ̀rẹ̀ nìyí: “Òwe Sólómọ́nì ọmọkùnrin Dáfídì, ọba Ísírẹ́lì, fún ènìyàn láti mọ ọgbọ́n àti ìbáwí, láti fi òye mọ àwọn àsọjáde òye, láti gba ìbáwí tí ń fúnni ní ìjìnlẹ̀ òye, òdodo àti ìdájọ́ àti ìdúróṣánṣán, láti fún àwọn aláìní ìrírí ní ìfọgbọ́nhùwà, láti fún ọ̀dọ́kùnrin ní ìmọ̀ àti agbára láti ronú.”—Òwe 1:1-4.
-
-
Ní Ọgbọ́n, Kí O Sì Gba ÌbáwíIlé Ìṣọ́—1999 | September 15
-
-
Àwọn onílàákàyè máa ń fọgbọ́n hùwà—kò rọrùn láti tètè tàn wọ́n jẹ. (Òwe 14:15) Kí wàhálà tó dé, wọ́n á ti rí i, wọ́n á sì ti gbára dì. Ọgbọ́n sì ń ràn wá lọ́wọ́ láti gbé ìrònú tó gbámúṣé kalẹ̀, èyí tó lè fúnni ní ìdarí tó nítumọ̀ nínú ìgbésí ayé. Kíkọ́ nípa àwọn òwe inú Bíbélì ṣàǹfààní púpọ̀, nítorí pé, a kọ ọ́ sílẹ̀ kí a bàa lè mọ ọgbọ́n àti ìbáwí. Kódà “àwọn aláìní ìrírí” tó bá fiyè sí òwe wọ̀nyí yóò ní ọgbọ́n tí wọ́n lè fi hùwà, “ọ̀dọ́kùnrin” tó bá sì lò ó yóò ní ìmọ̀ àti agbára láti ronú.
-