-
“Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
-
-
Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí baba tó fẹ́ràn ọmọ ẹ̀, Sólómọ́nì Ọba ọlọ́gbọ́n tó jẹ ní Ísírẹ́lì láyé ọjọ́un sọ pé: “Ọmọ mi, bí ìwọ yóò bá gba àwọn àsọjáde mi, tí ìwọ yóò sì fi àwọn àṣẹ tèmi ṣúra sọ́dọ̀ rẹ, láti lè dẹ etí rẹ sí ọgbọ́n, kí o lè fi ọkàn-àyà rẹ sí ìfòyemọ̀; jù bẹ́ẹ̀ lọ, bí o bá ké pe òye, tí o sì fọ ohùn rẹ jáde sí ìfòyemọ̀, bí o bá ń bá a nìṣó ní wíwá a bí fàdákà, tí o sì ń bá a nìṣó ní wíwá a kiri bí àwọn ìṣúra fífarasin, bí ọ̀ràn bá rí bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò lóye ìbẹ̀rù Jèhófà, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run gan-an.”—Òwe 2:1-5.
-
-
“Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
-
-
Àwọn ọ̀rọ̀ bíi “gbà,” “fi ṣúra,” “ké pe,” “bá a nìṣó ní wíwá,” “bá a nìṣó ní wíwá kiri” ló tẹ̀ lé gbólóhùn náà, “bí ó bá,” táa sọ ní àsọtúnsọ nínú àwọn ẹsẹ àkọ́kọ́ inú orí kejì ìwé Òwe. Èé ṣe tí òǹkọ̀wé yìí fi lo àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tó jẹ mọ́ ṣíṣe akitiyan níhìn-ín? Ìwé kan táa ṣèwádìí nínú rẹ̀ wí pé: “[Níhìn-ín] amòye náà ń tẹnu mọ́ bí ṣíṣaápọn nínú lílépa ọgbọ́n ti pọndandan tó.” Bẹ́ẹ̀ ni, a gbọ́dọ̀ ṣaápọn láti lépa ọgbọ́n àti àwọn ànímọ́ mìíràn tó tan mọ́ ọn—ìyẹn ni ìfòyemọ̀ àti òye.
Ṣé Wàá Sapá?
Kókó pàtàkì nínú lílépa ọgbọ́n ni fífi taápọntaápọn kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Ṣùgbọ́n, ẹ̀kọ́ yìí kò ní wulẹ̀ jẹ́ kíkàwé wuuruwu lásán torí ká ṣáà lè mọ nǹkan kan. Ṣíṣàṣàrò pẹ̀lú ète kan lọ́kàn ṣe pàtàkì táa bá ń kẹ́kọ̀ọ́ nínú Ìwé Mímọ́. Jíjèrè ọgbọ́n àti ìfòyemọ̀ wé mọ́ ṣíṣàṣàrò lórí báa ṣe lè lo ohun táa ti kọ́ láti lè yanjú ìṣòro tàbí láti ṣèpinnu. Jíjèrè òye ń béèrè fún ríronú lórí bí ọ̀rọ̀ tuntun náà ṣe bá ohun táa ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ mu. Ta ló wá lè jiyàn pé irú ìkẹ́kọ̀ọ́ tó gbàrònú nínú Bíbélì bẹ́ẹ̀ kò béèrè àkókó àti ìsapá tó gbagbára? Lílo àkókò àti agbára wá dà bí lílo àkókò àti agbára ‘nínú wíwá ohun ìṣúra fífarasin kiri.’ Ṣé wàá sapá? Ṣé wàá ‘ra àkókò tí ó rọgbọ padà’ láti ṣe bẹ́ẹ̀?—Éfésù 5:15, 16.
-