ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Nífẹ̀ẹ́ Àwọn Tí Ọlọ́run Fẹ́ràn
    ‘Ẹ Dúró Nínú Ìfẹ́ Ọlọ́run’
    • 2 Òótọ́ pọ́ńbélé lọ̀rọ̀ tí Bíbélì sọ pé: “Ẹni tí ó bá ń bá àwọn ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́n, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń ní ìbálò pẹ̀lú àwọn arìndìn yóò rí láburú.” (Òwe 13:20) Ohun tí òwe yìí sọ kọjá wíwulẹ̀ mọ ẹnì kan lóréfèé. Gbólóhùn náà ‘ń bá rìn’ túmọ̀ sí àjọṣe tó ń bá a nìṣó.a Nígbà tí ìwé kan tó dá lórí Bíbélì, èyí tá a ṣèwádìí nínú rẹ̀ máa sọ ọ́, ó ní: “Bíbá ẹnì kan rìn fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ onítọ̀hún, àti pé àjọṣe kan wà láàárín wa.” Àbí ìwọ náà ò mọ̀ pé a máa ń fẹ́ fara wé àwọn tá a bá fẹ́ràn? Ká sòótọ́, torí pé ọ̀dọ̀ àwọn tá a fẹ́ràn lọkàn wa máa ń wà lọ́pọ̀ ìgbà, ipa kékeré kọ́ ni wọ́n máa ń ní lórí wa, yálà sí rere tàbí búburú.

  • Nífẹ̀ẹ́ Àwọn Tí Ọlọ́run Fẹ́ràn
    ‘Ẹ Dúró Nínú Ìfẹ́ Ọlọ́run’
    • a Ọ̀rọ̀ Hébérù tá a tú sí “ní ìbálò pẹ̀lú” làwọn kan tún túmọ̀ sí “bá kẹ́gbẹ́” àti ‘bá rìn.’—Àwọn Onídàájọ́ 14:20; Òwe 22:24, Bibeli Ajuwe.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́