-
“Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
-
-
Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí baba tó fẹ́ràn ọmọ ẹ̀, Sólómọ́nì Ọba ọlọ́gbọ́n tó jẹ ní Ísírẹ́lì láyé ọjọ́un sọ pé: “Ọmọ mi, bí ìwọ yóò bá gba àwọn àsọjáde mi, tí ìwọ yóò sì fi àwọn àṣẹ tèmi ṣúra sọ́dọ̀ rẹ, láti lè dẹ etí rẹ sí ọgbọ́n, kí o lè fi ọkàn-àyà rẹ sí ìfòyemọ̀; jù bẹ́ẹ̀ lọ, bí o bá ké pe òye, tí o sì fọ ohùn rẹ jáde sí ìfòyemọ̀, bí o bá ń bá a nìṣó ní wíwá a bí fàdákà, tí o sì ń bá a nìṣó ní wíwá a kiri bí àwọn ìṣúra fífarasin, bí ọ̀ràn bá rí bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò lóye ìbẹ̀rù Jèhófà, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run gan-an.”—Òwe 2:1-5.
-
-
“Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
-
-
Ronú nípa ohun ìṣúra ńláǹlà tí a óò rí báa bá fòótọ́ inú ṣèwádìí jinlẹ̀ nínú Bíbélì. Họ́wù, a óò rí “ìmọ̀ Ọlọ́run gan-an”—ìmọ̀ tó yè kooro, tó fìdí múlẹ̀, ìmọ̀ tí ń fúnni ní ìyè, nípa Ẹlẹ́dàá wa! (Jòhánù 17:3) “Ìbẹ̀rù Jèhófà” tún jẹ́ ìṣúra táa lè jèrè. Ẹ ò rí i bí níní ìbẹ̀rù ọlọ́wọ̀ fún un ṣe ṣeyebíye tó! Ìbẹ̀rù tó gbámúṣé tí kì í jẹ́ ká ṣe ohun tí Jèhófà kò fẹ́ gbọ́dọ̀ máa darí gbogbo apá ìgbésí ayé wa, kó máa fi ìjẹ́pàtàkì tẹ̀mí kún gbogbo ohun tí a bá ń ṣe.—Oníwàásù 12:13.
-