ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • “Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”
    Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
    • Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí baba tó fẹ́ràn ọmọ ẹ̀, Sólómọ́nì Ọba ọlọ́gbọ́n tó jẹ ní Ísírẹ́lì láyé ọjọ́un sọ pé: “Ọmọ mi, bí ìwọ yóò bá gba àwọn àsọjáde mi, tí ìwọ yóò sì fi àwọn àṣẹ tèmi ṣúra sọ́dọ̀ rẹ, láti lè dẹ etí rẹ sí ọgbọ́n, kí o lè fi ọkàn-àyà rẹ sí ìfòyemọ̀; jù bẹ́ẹ̀ lọ, bí o bá ké pe òye, tí o sì fọ ohùn rẹ jáde sí ìfòyemọ̀, bí o bá ń bá a nìṣó ní wíwá a bí fàdákà, tí o sì ń bá a nìṣó ní wíwá a kiri bí àwọn ìṣúra fífarasin, bí ọ̀ràn bá rí bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò lóye ìbẹ̀rù Jèhófà, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run gan-an.”—Òwe 2:1-5.

  • “Jèhófà Fúnra Rẹ̀ Ní Ń Fúnni Ní Ọgbọ́n”
    Ilé Ìṣọ́—1999 | November 15
    • Ronú nípa ohun ìṣúra ńláǹlà tí a óò rí báa bá fòótọ́ inú ṣèwádìí jinlẹ̀ nínú Bíbélì. Họ́wù, a óò rí “ìmọ̀ Ọlọ́run gan-an”—ìmọ̀ tó yè kooro, tó fìdí múlẹ̀, ìmọ̀ tí ń fúnni ní ìyè, nípa Ẹlẹ́dàá wa! (Jòhánù 17:3) “Ìbẹ̀rù Jèhófà” tún jẹ́ ìṣúra táa lè jèrè. Ẹ ò rí i bí níní ìbẹ̀rù ọlọ́wọ̀ fún un ṣe ṣeyebíye tó! Ìbẹ̀rù tó gbámúṣé tí kì í jẹ́ ká ṣe ohun tí Jèhófà kò fẹ́ gbọ́dọ̀ máa darí gbogbo apá ìgbésí ayé wa, kó máa fi ìjẹ́pàtàkì tẹ̀mí kún gbogbo ohun tí a bá ń ṣe.—Oníwàásù 12:13.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́